Publicidade

Coração

Por Bíblia Online

O coração é o centro do ser humano — sede dos pensamentos, emoções e decisões. A Bíblia ensina a guardar, purificar e render o coração a Deus como oferta viva.

Guardar o coração

Sobre tudo o que se deve guardar, guarda o teu coração, porque dele procedem as fontes da vida e de toda decisão.

Ju gbogbo nǹkan tókù lọ, pa ọkàn rẹ mọ́,

nítorí òun ni orísun ìyè.

Ju gbogbo nǹkan tókù lọ, pa ọkàn rẹ mọ́,

nítorí òun ni orísun ìyè.

Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ

má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ.

Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ

má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ.

Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ

òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.

Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi.

Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.

Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà,

ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.

Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé

so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ,

kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.

Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere

ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.

Ọkàn tí ó lálàáfíà fi ìyè mú kí ọjọ́ ayé gùn fún ara,

ṣùgbọ́n ìlara mú kí egungun jẹrà.

Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ,

ṣùgbọ́n ètè wérewère yóò parun.

Coração puro

Cria em mim um coração puro, ó Deus. Ensina-me a contar meus dias para que tenha um coração sábio.

Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run,

kí o sì tún ẹ̀mí dídúró ṣinṣin ṣe sínú mi.

Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run,

kí o sì tún ẹ̀mí dídúró ṣinṣin ṣe sínú mi.

Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára,

kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.

Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi àti àṣàrò ọkàn mi

kí ó jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú rẹ,

Ìwọ Olúwa àpáta mi, àti Olùdáǹdè mi.

Jẹ́ alágbára, yóò sì mú yín ní àyà le

gbogbo ẹ̀yin tí ó dúró de Olúwa.

Ṣe inú dídùn sí Olúwa;

òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.

Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ

kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.

Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́

tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.

Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin

bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.

Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi

má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.

Buscar a Deus de coração

Amarás ao Senhor teu Deus de todo o coração. A busca sincera leva ao encontro; o coração dividido leva à ruína.

Jesu dáhùn pé, " ‘Fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, gbogbo ẹ̀mí rẹ àti gbogbo inú rẹ.

Jesu dáhùn pé, " ‘Fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, gbogbo ẹ̀mí rẹ àti gbogbo inú rẹ.

Nítorí ibi tí ìṣúra yín bá wà níbẹ̀ náà ni ọkàn yín yóò wà pẹ̀lú.

Lóòótọ́ ni mò wí fún un yín, bí ẹnikẹ́ni bá wí fún òkè ‘Ṣídìí, gbé ara rẹ sọ sínú Òkun,’ ti kò sì ṣe iyèméjì nínú ọkàn rẹ̀ ṣùgbọ́n tí ó gbàgbọ́ pé ohun tí òun wí yóò ṣẹ, yóò rí bẹ́ẹ̀ fún un.

Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ,

ó kọjá ohun tí a lè wòsàn.

Ta ni èyí lè yé?

Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ,

ó kọjá ohun tí a lè wòsàn.

Ta ni èyí lè yé?

"Èmi Olúwa ń wo ọkàn

àti èrò inú ọmọ ènìyàn,

láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀,

àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀."

Ẹ̀yin yóò wá mi, bí ẹ̀yin bá sì fi gbogbo ọkàn yín wá mi: ẹ̀yin yóò rí mi ni Olúwa Ọlọ́run wí.

Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín."

Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.

Èmi yóò fún yín ni ọkàn tuntun, èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú yín; Èmi yóò sì mú ọkàn òkúta kúrò nínú yín, èmi yóò sì fi ọkàn ẹran fún yín.

Conhecer o coração

O homem olha para a aparência, mas o Senhor olha para o coração. Deus conhece os segredos mais profundos.

Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Samuẹli pé, "Má ṣe wo ti ìrísí rẹ̀ tàbí ti gíga rẹ̀, nítorí èmi ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Olúwa kì í wo ohun tí ènìyàn máa ń wò. Ènìyàn máa ń wo òde ara ṣùgbọ́n Olúwa máa ń wo ọkàn."

Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Samuẹli pé, "Má ṣe wo ti ìrísí rẹ̀ tàbí ti gíga rẹ̀, nítorí èmi ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Olúwa kì í wo ohun tí ènìyàn máa ń wò. Ènìyàn máa ń wo òde ara ṣùgbọ́n Olúwa máa ń wo ọkàn."

Bí omi tí ń ṣe àfihàn ojú, nígbà tí a bá wò ó

bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ènìyàn ń ṣe àfihàn ènìyàn.

Ọkàn tí ó túká jẹ́ oògùn gidi,

ṣùgbọ́n ọkàn tí ó bàjẹ́ a máa mú kí egungun gbẹ.

Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé Olúwa lọ́wọ́,

èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.

Kí ọ̀ṣọ́ yín má ṣe jẹ́ ọ̀ṣọ́ òde, tí irun dídì, àti wúrà lílò, tàbí ti aṣọ wíwọ̀; ṣùgbọ́n kí ó jẹ́ ẹni tí ó fi ara sin ní ọkàn, nínú ọ̀ṣọ́ àìdíbàjẹ́ ti ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ àti ẹ̀mí tútù, èyí tí i ṣe iyebíye níwájú Ọlọ́run.

Kí olúkúlùkù ènìyàn ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti pinnu ní ọkàn rẹ̀; kì í ṣe àfi ìkùnsínú ṣe, tàbí ti àìgbọdọ̀ má ṣe; nítorí Ọlọ́run fẹ́ onínúdídùn ọlọ́rẹ.

Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ni fún Ọlọ́run pé, bí ẹ̀yin ti jẹ́ ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ rí, ẹ̀yin jẹ́ olùgbọ́ran láti ọkàn wá sí àpẹẹrẹ ẹ̀kọ́ èyí tí Ọlọ́run fi lé yín lọ́wọ́.

Kí ó lè fi ọkàn yín balẹ̀ ní àìlábùkù nínú ìwà mímọ́ níwájú Ọlọ́run àti Baba wa. Nígbà náà, ẹ ó ní ìgboyà láti dúró níwájú rẹ̀ láìṣẹ̀, ní ọjọ́ tí Olúwa wa Jesu Kristi yóò padà wá pẹ̀lú àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀.

ẹ má ṣe sé ọkàn yín le,

bí ìgbà ìṣọ̀tẹ̀,

bí i ní ọjọ́ ìdánwò ní aginjù,

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-22_10-02-25-