Publicidade

Intimidade com Deus

Por Bíblia Online

A intimidade com Deus é o maior privilégio do cristão. Ele nos convida a nos aproximar, a conhecê-lo profundamente e a desfrutar de comunhão diária com o Criador do universo.

Aproximar-se de Deus

Chegai-vos a Deus e Ele se chegará a vós. Deus deseja intimidade, não religiosidade. Ele busca os que o buscam de todo coração.

Ẹ súnmọ́ Ọlọ́run, òun ó sì súnmọ́ yín. Ẹ wẹ ọwọ́ yín mọ́, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀; ẹ sì ṣe ọkàn yín ní mímọ́, ẹ̀yin oníyèméjì.

"Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin tí òǹgbẹ ń gbẹ,

ẹ wá sí ibi omi;

àti ẹ̀yin tí kò ní owó;

ẹ wá, ẹ rà kí ẹ sì jẹ!

Ẹ wá ra wáìnì àti wàrà

láìsí owó àti láìdíyelé.

Èéṣe tí ẹ fi ń ná owó fún èyí tí kì í ṣe àkàrà

àti làálàá yín lórí ohun tí kì í tẹ́nilọ́rùn?

Tẹ́tí sílẹ̀, tẹ́tí sí mi, kí ẹ sì jẹ èyí tí ó dára,

bẹ́ẹ̀ ni ọkàn yín yóò láyọ̀ nínú ọrọ̀ tí ó bójúmu.

Tẹ́tí sílẹ̀ kí o sì wá sọ́dọ̀ mi;

gbọ́ tèmi, kí ọkàn rẹ lè wà láààyè.

Èmi yóò dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú rẹ,

ìfẹ́ òtítọ́ tí mo ṣèlérí fún Dafidi.

Kíyèsi i, mo ti fi òun ṣe ẹlẹ́rìí fún àwọn ènìyàn,

olórí àti apàṣẹ fún àwọn ènìyàn.

Lóòtítọ́ ìwọ yóò ké sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀

àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ ni yóò sáré tọ̀ ọ́ wá,

nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ

Ẹni Mímọ́ Israẹli

nítorí pé ó ti fi ohun dídára dá ọ lọ́lá."

Ẹ wá Olúwa nígbà tí ẹ lè rí i;

ẹ pè é nígbà tí ó wà nítòsí.

Kí wọn tó pè, èmi yóò dáhùn;

nígbà tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, èmi yóò gbọ́.

‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’

Nítorí mo mọ èrò tí mo rò sí yín," ni Olúwa wí, "àní èrò àlàáfíà, kì í sì ṣe fún ibi, èrò láti fún un yín ní ìgbà ìkẹyìn àti ìrètí ọjọ́ iwájú.

Sede de Deus

Como a corça deseja as correntes de água, assim a minha alma suspira por ti, ó Deus. A intimidade nasce do desejo profundo.

Bí àgbọ̀nrín ti ń mí hẹlẹ sí ipa odò omi,

bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń mí hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run.

Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè.

Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?

Ọlọ́run, ìwọ ni Ọlọ́run mi,

nígbà gbogbo ni mo ń ṣàfẹ́rí rẹ,

òǹgbẹ rẹ ń gbẹ ọkàn mi,

ara mi fà sí ọ,

ní ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tí ń ṣàárẹ̀

níbi tí kò sí omi.

Èmi ti rí ọ ní ibi mímọ́,

mo rí agbára àti ògo rẹ.

Nítorí ìfẹ́ rẹ dára ju ayé lọ,

ètè mi yóò fògo fún ọ.

Èmi ó yìn ọ́ níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè,

èmi ó gbé ọwọ́ sókè, èmi ó sì pe orúkọ rẹ.

A ó tẹ́ ọkàn mi lọ́rùn bí ọlọ́ràá oúnjẹ;

pẹ̀lú ètè ìyìn, ẹnu mi yóò yìn ọ́.

Nígbà tí mo rántí rẹ lórí ibùsùn mi;

èmi ń ronú rẹ títí ìṣọ́ òru.

Nítorí ìwọ ni ìrànlọ́wọ́ mi,

mo kọrin níbi òjìji ìyẹ́ apá rẹ.

Ọkàn mí fà sí ọ:

ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbé mi ró.

Àwọn tí ó ń wá ọkàn mí ni a ó parun;

wọn ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé.

Wọn ó ti ọwọ́ idà ṣubú

wọn ó sì di jíjẹ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀.

Ṣùgbọ́n ọba yóò yọ̀ nínú Ọlọ́run

ẹni tí ó fi orúkọ Ọlọ́run búra yóò ṣògo

ṣùgbọ́n ẹnu àwọn òpùrọ́ la ó pamọ́.

Unidade com o Pai

Jesus orou pela unidade dos seus com o Pai. A intimidade com Deus inclui confissão, perdão e alegria na comunhão.

Ògo tí ìwọ ti fi fún mi ni èmi sì ti fi fún wọn; kí wọn kí ó lè jẹ́ ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí àwa ti jẹ́ ọ̀kan. Èmi nínú wọn, àti ìwọ nínú mi, kí a lè ṣe wọ́n pé ní ọ̀kan; kí ayé kí ó lè mọ̀ pé, ìwọ ni ó rán mi, àti pé ìwọ sì fẹ́ràn wọn gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti fẹ́ràn mi.

Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ,

Ó ní agbára láti gbà ọ là.

Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀;

Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀,

Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ."

Bí àwa bá jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wa, olóòtítọ́ àti olódodo ni òun láti dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá, àti láti wẹ̀ wá nù kúrò nínú àìṣòdodo gbogbo.

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-22_10-02-25-