Ìyá Jesu àti àwọn arákùnrin rẹ̀
46 12.46-50: Mk 3.31-35; Lk 8.19-21. 12.46: Jh 2.1-12; 19.25-27; 7.1-10; Mk 6.3; 1Kọ 9.5. Nígbà tí ó ń sọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn, wò ó, ìyá rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ dúró lóde, wọ́n fẹ́ bá a sọ̀rọ̀. 47 Nígbà náà ni ẹnìkan wí fún un pé, "Ìyá rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ ń dúró dè ọ́ lóde wọ́n ń fẹ́ bá ọ sọ̀rọ̀."
48 Ó sì fún ni èsì pé, "Ta ni ìyá mi? Ta ni àwọn arákùnrin mi?" 49 Ó nawọ́ sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó wí pé, "Wò ó, ìyá mi àti àwọn arákùnrin mi ni wọ̀nyí." 50 12.50: Jh 15.14.Nítorí náà, "Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe ìfẹ́ Baba mi tí ń bẹ ní ọ̀run, ni arákùnrin mi àti arábìnrin mi àti ìyá mi."