16 Nígbà tí ó di àṣálẹ́, ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó ní ẹ̀mí èṣù ni a mú wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ lé àwọn ẹ̀mí èṣù náà jáde. A sì mú gbogbo àwọn ọlọ́kùnrùn láradá. 17 8.17: Isa 53.4.Kí èyí tí a ti sọ láti ẹnu wòlíì Isaiah lè ṣẹ pé,
"Òun tìkára rẹ̀ gbà àìlera wa,
ó sì ń ru ààrùn wa."