23 Bí a ti tún yín bí, kì í ṣe láti inú ìdíbàjẹ́ wá, bí kò ṣe èyí ti kì í díbàjẹ́ nípa ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí ń bẹ láààyè tí ó sì dúró. 24 1.24-25: Isa 40.6-9.Nítorí pé,
"Gbogbo ènìyàn dàbí koríko,
àti gbogbo ògo rẹ̀ bi ìtànná koríko.
Koríko á máa gbẹ ìtànná a sì máa rẹ̀ dànù,
25 ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Olúwa dúró títí láé."
Ọ̀rọ̀ náà yìí sì ni ìyìnrere tí a wàásù fún yín.