Publicidade

Eclesiastes 4

Ìnilára, làálàá, àti àìlọ́rẹ̀ẹ́

1 Mo sì tún wò ó, mo sì rí gbogbo ìnilára tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn,

mo rí ẹkún àwọn tí ara ń ni,

wọn kò sì ní olùtùnú kankan,

agbára wà ní ìkápá àwọn tí ó ń ni wọ́n lára,

wọn kò sì ní olùtùnú kankan.

2 Mo jowú àwọn tí wọ́n ti kú

tí wọ́n sì ti lọ,

ó sàn fún wọn ju àwọn

tí wọ́n sì wà láààyè lọ.

3 Nítòótọ́, ẹni tí kò tí ì sí sàn ju

àwọn méjèèjì lọ:

ẹni tí kò tí ì rí iṣẹ́ búburú

tí ó ń lọ ní abẹ́ oòrùn.

4 Mo sì tún mọ̀ pẹ̀lú, ìdí tí ènìyàn fi ń ṣiṣẹ́ tagbára tagbára láti ṣe àṣeyọrí, nítorí pé wọn ń jowú àwọn aládùúgbò wọn ni. Ṣùgbọ́n, asán ni, ó dàbí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́.

5 Aṣiwèrè ká ọwọ́ rẹ̀ kò

ó sì ba tara rẹ̀ jẹ́.

6 Oúnjẹ ẹ̀kúnwọ́ kan pẹ̀lú ìdákẹ́ jẹ́ẹ́jẹ́ sàn ju ẹ̀kúnwọ́ méjì pẹ̀lú wàhálà,

àti gbígba ìyànjú àti lé afẹ́fẹ́ lọ.

7 Lẹ́ẹ̀kan sí i, mo tún rí ohun asán kan lábẹ́ oòrùn.

8 Ọkùnrin kan ṣoṣo dá wà;

kò ní ọmọkùnrin kankan tàbí ẹbí.

Kò sí òpin nínú làálàá rẹ̀ gbogbo,

síbẹ̀, ọrọ̀ kò tẹ́ ojú rẹ̀ lọ́rùn.

Bẹ́ẹ̀ ni kò sì wí pé, "Nítorí ta ni èmí ṣe ń ṣe làálàá,

àti wí pé, èétiṣe tí mo fi ń fi ìgbádùn du ara mi?"

Eléyìí náà asán ni,

iṣẹ́ òsì!

9 Ẹni méjì sàn ju ẹnìkan,

nítorí wọ́n ní èrè rere fún làálàá wọn.

10 Tí ọ̀kan bá ṣubú lulẹ̀,

ọ̀rẹ́ rẹ̀ le è ràn án lọ́wọ́ kí ó fà á sókè,

ṣùgbọ́n ìyọnu ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣubú

tí kò sì ní ẹni tí ó le è ràn án lọ́wọ́!

11 Àti pẹ̀lú pé, bí ẹni méjì bá sùn pọ̀, wọn yóò móoru.

Ṣùgbọ́n báwo ni ẹnìkan ṣe le è dá nìkan móoru?

12 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a le è kojú ogun ẹnìkan,

àwọn méjì le è gbìjà ara wọn,

ìkọ́ okùn mẹ́ta kì í dùn ún yára fà já.

Asán ni ipò gíga

13 Òtòṣì ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ tí ó ṣe ọlọ́gbọ́n, ó sàn ju arúgbó àti aṣiwèrè ọba lọ tí kò mọ bí yóò ti ṣe gba ìmọ̀ràn. 14 Nítorí pé láti inú túbú ni ó ti jáde láti jẹ ọba, bí a tilẹ̀ bí i ní tálákà ní ìjọba rẹ̀. 15 Mo rí gbogbo alààyè tí ń rìn lábẹ́ oòrùn, pẹ̀lú ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ kejì tí yóò gba ipò ọba yìí. 16 Gbogbo àwọn tí ó wà níwájú wọn kò sì lópin, ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn ní ó jẹ ọba lé lórí, ẹni tí ó wà ní ipò yìí kò dùn mọ́ àwọn tí ó tẹ̀lé wọn nínú. Asán ni eléyìí pẹ̀lú jẹ́, ó dàbí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.

Veja também

Publicidade
Eclesiastes
Ver todos os capítulos de Eclesiastes
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-