Publicidade

Eclesiastes 11

Àkàrà lórí omi

1 Fún àkàrà rẹ sórí omi,

nítorí lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ìwọ yóò rí i padà.

2 Fi ìpín fún méje, àní fún mẹ́jọ pẹ̀lú,

nítorí ìwọ kò mọ ohun ìparun tí ó le è wá sórí ilẹ̀.

3 Bí àwọsánmọ̀ bá kún fún omi,

ayé ni wọ́n ń rọ òjò sí.

Bí igi wó sí ìhà gúúsù tàbí sí ìhà àríwá,

níbi tí ó wó sí náà, ni yóò dùbúlẹ̀ sí.

4 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wo afẹ́fẹ́ kò ní fúnrúgbìn;

ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wo àwọsánmọ̀ kò ní kórè.

5 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ kò ti ṣe mọ ojú ọ̀nà afẹ́fẹ́

tàbí mọ bí ọmọ tí ń dàgbà nínú ikùn ìyáarẹ̀,

bẹ́ẹ̀ náà ni ìwọ kò le è ní òye iṣẹ́ Ọlọ́run

ẹlẹ́dàá ohun gbogbo.

6 Fún irúgbìn rẹ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù,

má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣọlẹ̀ ní àṣálẹ́,

nítorí ìwọ kò mọ èyí tí yóò ṣe rere

bóyá èyí tàbí ìyẹn

tàbí àwọn méjèèjì ni yóò ṣe dáradára bákan náà.

Rántí ẹlẹ́dàá rẹ ní ìgbà èwe rẹ

7 Ìmọ́lẹ̀ dùn;

Ó sì dára fún ojú láti rí oòrùn.

8 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn jẹ̀gbádùn gbogbo iye ọdún

tí ó le è lò láyé

ṣùgbọ́n jẹ́ kí ó rántí ọjọ́ òkùnkùn

nítorí wọn ó pọ̀.

Gbogbo ohun tí ó ń bọ̀ asán ni.

9 Jẹ́ kí inú rẹ dùn, ìwọ ọ̀dọ́mọdé ní ìgbà tí o wà ní èwe

kí o sì jẹ́ kí ọkàn rẹ fún ọ ní ayọ̀ ní ìgbà èwe rẹ.

Tẹ̀lé ọ̀nà ọkàn rẹ

àti ohunkóhun tí ojú rẹ rí

ṣùgbọ́n mọ̀ dájú pé nípa gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni

Ọlọ́run yóò mú ọ wá sí ìdájọ́.

10 Nítorí náà, mú ìjayà kúrò ní ọkàn rẹ

kí o sì lé ìbànújẹ́ ara rẹ kúrò

nítorí èwe àti kékeré kò ní ìtumọ̀.

Veja também

Publicidade
Eclesiastes
Ver todos os capítulos de Eclesiastes
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-