21 Nígbà náà, ni Marta wí fún Jesu pé, "Olúwa, ìbá ṣe pé ìwọ ti wà níhìn-ín, arákùnrin mi kì bá kú. 22 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí náà, mo mọ̀ pé, ohunkóhun tí ìwọ bá béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, Ọlọ́run yóò fi fún ọ."
23 Jesu wí fún un pé, "Arákùnrin rẹ yóò jíǹde."
24 11.24: Da 12.2; Jh 5.28; Ap 24.15. Marta wí fún un pé, "Mo mọ̀ pé yóò jíǹde ní àjíǹde ìkẹyìn."
25 11.25: Jh 1.4; 5.26; If 1.18. Jesu wí fún un pé, "Èmi ni àjíǹde àti ìyè, ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, bí ó tilẹ̀ kú, yóò yè. 26 11.26: Jh 6.47; 8.51.Ẹnikẹ́ni tí ó ń bẹ láààyè, tí ó sì gbà mí gbọ́, kì yóò kú láéláé ìwọ gbà èyí gbọ́?"
27 11.27: Mt 16.16. Ó wí fún un pé, "Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, èmi gbàgbọ́ pé, ìwọ ni Kristi náà Ọmọ Ọlọ́run, ẹni tí ń bọ̀ wá sí ayé."