32 Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, "Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kì í ṣe Mose ni ó fi oúnjẹ fún yín láti ọ̀run wá, ṣùgbọ́n Baba mi ni ó fi oúnjẹ òtítọ́ náà fún yín láti ọ̀run wá. 33 Nítorí pé oúnjẹ Ọlọ́run ni èyí tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, tí ó sì fi ìyè fún aráyé."
34 6.34: Jh 4.15; Mt 6.11. Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, "Olúwa, máa fún wa ní oúnjẹ yìí títí láé."
35 6.35: Jh 6.48-50; 4.14. Jesu wí fún wọn pé, "Èmi ni oúnjẹ ìyè, ẹnikẹ́ni tí ó bá tọ̀ mí wá, ebi kì yóò pa á; ẹni tí ó bá sì gbà mí gbọ́, òǹgbẹ kì yóò gbẹ ẹ́ mọ́ láé.