Jesu la ojú ẹni tí a bí ní afọ́jú
1 Bí ó sì ti ń kọjá lọ, ó rí ọkùnrin kan tí ó fọ́jú láti ìgbà ìbí rẹ̀ wá. 2 9.2: Lk 13.2; Ap 28.4; El 18.20; El 20.5.Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì bi í léèrè, pé, "Rabbi, ta ní ó dẹ́ṣẹ̀, ọkùnrin yìí tàbí àwọn òbí rẹ̀, tí a fi bí i ní afọ́jú?"
3 9.3: Jh 11.4. Jesu dáhùn pé, "Kì í ṣe nítorí pé ọkùnrin yìí dẹ́ṣẹ̀, tàbí àwọn òbí rẹ̀: ṣùgbọ́n kí a ba à lè fi iṣẹ́ Ọlọ́run hàn lára rẹ̀. 4 9.4: Jh 11.9; 12.35.Èmi ní láti ṣe iṣẹ́ ẹni tí ó rán mi, níwọ̀n ìgbà tí ó bá ti jẹ́ ọ̀sán, òru ń bọ̀ wá nígbà tí ẹnìkan kì yóò lè ṣe iṣẹ́. 5 9.5: Jh 1.4; 8.12; 12.46.Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè, èmi ni ìmọ́lẹ̀ ayé."
6 9.6: Mk 7.33; 8.23. Nígbà tí ó ti wí bẹ́ẹ̀ tan, ó tutọ́ sílẹ̀, ó sì fi itọ́ náà ṣe amọ̀, ó sì fi amọ̀ náà ra ojú afọ́jú náà. 7 9.7: Lk 13.4.Ó sì wí fún un pé, "Lọ wẹ̀ nínú adágún Siloamu!" (Ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ yìí ni "rán"). Nítorí náà ó gba ọ̀nà rẹ̀ lọ, ó wẹ̀, ó sì dé, ó ń ríran.