Ìwòsàn adẹ́tẹ̀ mẹ́wàá
11 17.11: Lk 9.51; 13.22; 19.11. Ó sì ṣe, bí ó ti ń lọ sí Jerusalẹmu, ó kọjá láàrín Samaria Galili. 12 17.12: Le 13.45-46.Bí ó sì ti ń wọ inú ìletò kan lọ, àwọn ọkùnrin adẹ́tẹ̀ mẹ́wàá pàdé rẹ̀, wọ́n dúró ní òkèrè, 13 17.13: Lk 5.5; 8.24,45; 9.33,49.wọ́n sì kígbe sókè wí pé, "Jesu, Olùkọ́, ṣàánú fún wa."
14 17.14: Lk 5.14; Mt 8.4; Mk 1.44; Le 14.2-32. Nígbà tí ó rí wọn, ó wí fún wọn pé, "Ẹ lọ í fi ara yín hàn fún àwọn àlùfáà." Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, wọ́n sì di mímọ́.
15 Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn rí i pé a mú òun láradá ó padà, ó sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run lógo. 16 Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ń dúpẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀: ará Samaria ni òun í ṣe.
17 Jesu sì dáhùn wí pé, "Àwọn mẹ́wàá kí a sọ di mímọ́? Àwọn mẹ́sàn-án ìyókù ha dà? 18 A kò rí ẹnìkan tí ó padà wá fi ògo fún Ọlọ́run, bí kò ṣe àlejò yìí?" 19 17.19: Mt 9.22; Mk 5.34; Lk 8.48; 18.42.Ó sì wí fún un pé, "Dìde, kí o sì máa lọ, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá."