Afọ́jú alágbe gba ìwòsàn
35 18.35-43: Mt 20.29-34; Mk 10.46-52; Mt 9.27-31; Mk 8.22; Jh 9.1-7. Bí ó ti súnmọ́ Jeriko, afọ́jú kan jókòó lẹ́bàá ọ̀nà ó ń ṣagbe. 36 Nígbà tí ó gbọ́ tí ọ̀pọ̀ ń kọjá lọ, ó béèrè pé, kín ni ìtumọ̀ èyí. 37 Wọ́n sì wí fún un pé, "Jesu ti Nasareti ni ó ń kọjá lọ."
38 Ó sì kígbe pé, "Jesu, ìwọ ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!"
39 Àwọn tí ń lọ níwájú bá a wí, pé, kí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n òun sì kígbe sókè sí í pé, "Ìwọ Ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!"
40 Jesu sì dúró, ó ní, kí á mú un tọ òun wá nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn, ó bi í 41 wí pé, "Kí ni ìwọ ń fẹ́ kí èmi ṣe fún ọ?"
Ó sì wí pé, "Olúwa jẹ́ kí èmi ríran."
42 18.42: Mt 9.22; Mk 5.34; 10.52; Lk 7.50; 8.48; 17.19. Jesu sì wí fún un pé, "Ríran; ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá." 43 Lójúkan náà ó sì ríran, ó sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo àti gbogbo ènìyàn nígbà tí wọ́n rí i, wọ́n fi ìyìn fún Ọlọ́run.