15 21.15: Lk 19.39; Mt 21.9.Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin rí àwọn iṣẹ́ ìyanu ńlá wọ̀nyí, ti wọ́n sì tún ń gbọ́ tí àwọn ọmọdé ń kígbe nínú tẹmpili pé, "Hosana fún ọmọ Dafidi," inú bí wọn.
16 21.16: Sm 8.2. Wọ́n sì bí i pé, "Ǹjẹ́ ìwọ gbọ́ nǹkan tí àwọn ọmọdé wọ̀nyí ń sọ?"
Jesu sí dáhùn pé, "Bẹ́ẹ̀ ni, àbí ẹ̀yin kò kà á pé,
" ‘Láti ẹnu àwọn ọmọdé àti àwọn ọmọ ọmú,
ni a ó ti máa yìn mí’?"