Misericórdia
A misericórdia de Deus é eterna e inesgotável. Ele se compadece dos que sofrem, perdoa os arrependidos e derrama graça sobre os que não merecem. Grande é a sua fidelidade.
A misericórdia de Deus
Quem é Deus como tu, que perdoa a iniquidade? Ele se deleita em ter misericórdia e não retém a ira para sempre.
Ta ni Ọlọrun bí rẹ,
ẹni tí ó dárí ẹṣẹ jì,
tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ?
Kì í dúró nínú ìbínú rẹ láéláé
nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
Ṣàánú fún mi, Ọlọrun,
gẹgẹ bí ìdúró ṣinṣin ìfẹ rẹ,
gẹgẹ bí ọpọ àánú rẹ
kí o sì pa gbogbo ẹṣẹ mi rẹ.
Wẹ gbogbo àìṣedéédéé mi nù kúrò
kí o sì wẹ mi mọ kúrò nínú ẹṣẹ mi!
Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ ẹ rẹ ńlá,
torí pé wọn ti wà ní ìgbà àtijọ.
Má ṣe rántí àwọn ẹṣẹ ìgbà èwe mi
tàbí ìrékọjá mi;
gẹgẹ bí i ìfẹ ẹ rẹ rántí mi
nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
Láti inú ibú wá ni
èmi ń ké pè é ọ Olúwa
Olúwa, gbóhùn mi,
jẹ kí etí rẹ kí o tẹ sílẹ sí ohùn ẹbẹ mi.
Ìwọ má ṣe, fa àánú rẹ tí ó rọnú sẹyìn kúrò lọdọ mi Olúwa;
jẹ kí ìṣeun ìfẹ rẹ àti òtítọ rẹ
kí ó máa pa mi mọ títí ayérayé.
Nítòótọ, ìre àti àánú ni yóò máa tọ mí lẹyìn
ní ọjọ ayé è mi gbogbo,
èmi yóò sì máa gbé inú ilé Olúwa
títí láéláé.
Bí baba ti ń ṣe ìyọnú sí àwọn ọmọ rẹ,
bẹẹ ni Olúwa ń ṣe ìyọnú sí àwọn tí ó bẹrù rẹ,
Graça e perdão
Onde o pecado abundou, superabundou a graça. Deus convida todos ao arrependimento e promete perdão total aos que confessam.
Ṣùgbọn ẹbùn ọfẹ kò dàbí ẹṣẹ. Nítorí bí nípa ẹṣẹ. Nítorí bí o bá jẹ pé ẹnìkan ẹni púpọ kú, mélòó mélòó ni oore-ọfẹ Ọlọrun, àti ẹbùn nínú oore-ọfẹ ọkùnrin kan, Jesu Kristi, di púpọ fún ẹni púpọ.
Ǹjẹ èyí túmọ sí pé, nísinsin yìí, a lè tẹsíwájú láti máa dẹṣẹ láìbìkítà, nítorí ìgbàlà wa kò dúró nípa òfin mọ, bí kò ṣe nípa gbígba oore-ọfẹ Ọlọrun!
Ṣùgbọn Ọlọrun, ẹni tí í ṣe ọlọrọ ni àánú, nítorí ìfẹ ńlá rẹ tí ó fi fẹ wa, nígbà tí àwa tilẹ ti kú nítorí ìrékọjá wa, ó sọ wá di ààyè pẹlú Kristi, oore-ọfẹ ni a ti fi gbà yín là.
Òun sì wí fún mi pé, "Oore-ọfẹ mi tó fún ọ, nítorí pé a sọ agbára mi di pípé nínú àìlera." Nítorí náà tayọtayọ ni èmi ó kúkú máa fi ṣògo nínú àìlera mi, kí agbára Kristi lè máa gbé inú mi.
Ẹni tí ó bo ẹṣẹ rẹ mọlẹ kì yóò ṣe rere,
ṣùgbọn ẹni tí ó bá jẹwọ tí ó sì kọ wọn sílẹ máa ń rí àánú gbà.
Jẹ kí ìkà kí ó kọ ọnà rẹ sílẹ
àti ènìyàn búburú èrò rẹ.
Jẹ kí ó yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì ṣàánú fún un,
àti sí Ọlọrun wa, nítorí Òun yóò sì dáríjì.
Síbẹsíbẹ Olúwa sì fẹ síjú àánú wò ọ;
ó dìde láti ṣàánú fún ọ.
Nítorí Olúwa jẹ Ọlọrun ìdájọ.
Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
Misericórdia e compaixão
Misericórdia quero e não sacrifício. Deus nos chama a ser misericordiosos como Ele é, perdoando e acolhendo o próximo.
Ṣùgbọn ẹ lọ kọ ohun ti èyí túmọ sí: ‘Àánú ni èmi ń fẹ, kì í ṣe ẹbọ,’ nítorí èmi kò wá láti pe àwọn olódodo, bí kò ṣe àwọn ẹlẹṣẹ."
Nígbà náà ni Peteru wá sọdọ Jesu, ó béèrè pé, "Olúwa, nígbà mélòó ni arákùnrin mi yóò ṣẹ mi, tí èmi yóò sì dáríjì í? Tàbí ní ìgbà méje ni?"
Jesu dáhùn pé, "Mo wí fún ọ, kì í ṣe ìgbà méje, ṣùgbọn ní ìgbà àádọrin méje.
Nítorí náà, bí ẹyin bá dárí jí àwọn tó ṣẹ yín, baba yín ọrun náà yóò dáríjì yín.
Ṣùgbọn nínú ọpọ àánú rẹ, ìwọ kò mú òpin bá wọn tàbí kọ wọn sílẹ, nítorí ìwọ ni Ọlọrun olóore-ọfẹ àti aláàánú.
Ènìyàn rere fi ojúrere hàn,
a sì wínni;
ìmòye ni yóò máa fi la ọnà iṣẹ rẹ.
Jẹ kí ẹwà Olúwa Ọlọrun wa wà lára wa;
fi ìdí iṣẹ ọwọ wa múlẹ lára wa,
bẹẹ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ ọwọ wa múlẹ.
Acessar a misericórdia
Cheguemos com confiança ao trono da graça. Ali encontramos misericórdia e graça para socorro no tempo oportuno.
Nítorí náà, ẹ jẹ kí a wá si ibi ìtẹ oore-ọfẹ pẹlú ìgboyà, kí a lè rí àánú gbà, kí a sì rí oore-ọfẹ láti máa ran ni lọwọ ní àkókò tí ó wọ.
Nítorí náà mo fi ìyọnú Ọlọrun bẹ yín ará, kí ẹyin kí ó fi ara yín fún Ọlọrun ní ẹbọ ààyè mímọ, ìtẹwọgbà, èyí ni iṣẹ ìsìn yín tí ó tọnà.
"Nítorí Ọlọrun fẹ aráyé tó bẹẹ gẹẹ, tí ó fi ọmọ rẹ kan ṣoṣo fún ni, kí ẹnikẹni tí ó bá gbà á gbọ, má bà á ṣègbé, ṣùgbọn kí ó lè ní ìyè àìnípẹkun.
Nítorí tí a ti fún yin ni àǹfààní, kì í ṣe láti gba Kristi gbọ nìkan, ṣùgbọn láti jìyà nítorí rẹ pẹlú.
Hesekiah sì ránṣẹ́ sí gbogbo Israẹli àti Juda, ó sì kọ ìwé sí Efraimu àti Manase, kí wọn kí ó wá sínú ilé Olúwa ní Jerusalẹmu láti pa àjọ ìrékọjá mọ́ sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Nítorí tí ọba ti gbìmọ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo ìjọ ènìyàn ní Jerusalẹmu, láti pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní oṣù kejì. Nítorí wọn kò lè pa á mọ́ ní àkókò náà, nítorí àwọn àlùfáà kò tí i ya ara wọn sí mímọ́ tó; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò tí ì kó ara wọn jọ sí Jerusalẹmu. Ọ̀rọ̀ náà sí tọ́ lójú ọba àti lójú gbogbo ìjọ ènìyàn. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi àṣẹ kan lélẹ̀, láti kéde ká gbogbo Israẹli láti Beerṣeba àní títí dé Dani, láti wá pa àjọ ìrékọjá mọ́ sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ní Jerusalẹmu: nítorí wọn kò pa á mọ́ ní ọjọ́ púpọ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́.
Bẹ́ẹ̀ àwọn oníṣẹ́ tí ń sáré lọ pẹ̀lú ìwé láti ọwọ́ ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ sí gbogbo Israẹli àti Juda; àti gẹ́gẹ́ bí àṣẹ ọba, wí pé,
"Ẹ̀yin ọmọ Israẹli ẹ yí padà sí Olúwa Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki, àti Israẹli, òun ó sì yípadà sí àwọn ìyókù nínú yín, tí ó sálà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria. Kí ẹ̀yin kí ó má sì ṣe dàbí àwọn baba yín, àti bí àwọn arákùnrin yín tí ó dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn, nítorí náà ní ó ṣe fi wọ́n fún ìdahoro bí ẹ̀yin ti rí. Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe ọlọ́rùn líle, bí àwọn baba yín, ṣùgbọ́n ẹ jọ̀wọ́ ara yín lọ́wọ́ fún Olúwa, kí ẹ sì wọ inú ibi mímọ́ rẹ̀ lọ, ti òun ti ìyàsímímọ́ títí láé. Kí ẹ sì sin Olúwa, Ọlọ́run yín kí gbígbóná ìbínú rẹ̀ kí ó lè yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ yín. Nítorí bí ẹ̀yin bá tún yípadà sí Olúwa, àwọn arákùnrin yín, àti àwọn ọmọ yín, yóò rí àánú níwájú àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, kí wọn kí ó lè tún padà wá sí ilẹ̀ yí: nítorí Olúwa Ọlọ́run yín, oníyọnu àti aláàánú ni, kì yóò sì yí ojú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ yín, bí ẹ̀yin bá padà sọ́dọ̀ rẹ̀."
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ náà kọjá láti ìlú dé ìlú, ní ilẹ̀ Efraimu àti Manase títí dé Sebuluni, ṣùgbọ́n wọ́n fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n sì gàn wọ́n. Síbẹ̀ òmíràn nínú àwọn ènìyàn Aṣeri àti Manase àti Sebuluni rẹ̀ ara wọn sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu. Ní Juda pẹ̀lú, ọwọ́ Ọlọ́run wá láti fún wọn ní ọkàn kan láti pa òfin ọba mọ́ àti tí àwọn ìjòyè, nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn sì péjọ ní Jerusalẹmu, láti pa àjọ àkàrà àìwú mọ́ ní oṣù kejì. Wọ́n sì dìde, wọ́n sì kó gbogbo pẹpẹ tí ó wà ní Jerusalẹmu lọ, àti gbogbo pẹpẹ tùràrí ni wọ́n kó lọ, wọ́n sì dà wọ́n sí odò Kidironi.
Nígbà náà ni wọ́n pa ẹran ìrékọjá náà ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì: ojú sì ti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì yà ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì mú ẹbọ sísun wá sínú ilé Olúwa. Wọ́n sì dúró ní ipò wọn, bí ètò wọn gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, ènìyàn Ọlọ́run: àwọn àlùfáà wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà, tí wọ́n gbà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Lefi. Nítorí pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó wà nínú ìjọ ènìyàn náà tí kò yà ara wọn sí mímọ́: nítorí náà ni àwọn ọmọ Lefi ṣe ń tọ́jú àti pa ẹran ìrékọjá fún olúkúlùkù ẹni tí ó ṣe aláìmọ́, láti yà á sí mímọ́ sí Olúwa. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú Efraimu àti Manase, Isakari, àti Sebuluni kò sá wẹ̀ ara wọn mọ́ síbẹ̀ wọ́n jẹ ìrékọjá náà, kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́. Ṣùgbọ́n Hesekiah bẹ̀bẹ̀ fún wọn, wí pé, Olúwa, ẹni rere, dáríjì olúkúlùkù, tí ó múra ọkàn rẹ̀ láti wá Ọlọ́run, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba rẹ̀ ṣùgbọ́n tí kì í ṣe nípa ìwẹ̀nùmọ́ mímọ́ Olúwa sì gbọ́ ti Hesekiah, ó sì mú àwọn ènìyàn náà láradá.
Àwọn ọmọ Israẹli tí a rí ní Jerusalẹmu fi ayọ̀ ńlá pa àjọ àkàrà àìwú mọ́ ní ọjọ́ méje: àwọn ọmọ Lefi, àti àwọn àlùfáà yin Olúwa lójoojúmọ́, wọ́n ń fi ohun èlò olóhùn gooro kọrin sí Olúwa.
Hesekiah sọ̀rọ̀ ìtùnú fún gbogbo àwọn ọmọ Lefi, tí ó lóye ní ìmọ̀ rere Olúwa: ọjọ́ méje ni wọ́n fi jẹ àsè náà wọ́n rú ẹbọ àlàáfíà, wọ́n sì ń fi ohùn rara dúpẹ́ fún Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn.
Gbogbo ìjọ náà sì gbìmọ̀ láti pa ọjọ́ méje mìíràn mọ́: wọ́n sì fi ayọ̀ pa ọjọ́ méje mìíràn mọ́. Nítorí Hesekiah, ọba Juda, ta ìjọ ènìyàn náà ní ọrẹ, ẹgbẹ̀rún (1,000) akọ màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin (7,000) àgùntàn. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn àlùfáà sì ya ara wọn sí mímọ́. Gbogbo ìjọ ènìyàn Juda pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó ti inú Israẹli jáde wá, àti àwọn àjèjì tí ó ti ilẹ̀ Israẹli jáde wá, àti àwọn tí ń gbé Juda yọ̀. Bẹ́ẹ̀ ni ayọ̀ ńlá sì wà ní Jerusalẹmu: nítorí láti ọjọ́ Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli, irú èyí kò sí ní Jerusalẹmu. Nígbà náà ni àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi dìde, wọ́n sì súre fún àwọn ènìyàn náà: a sì gbọ́ ohùn wọn, àdúrà wọn sì gòkè lọ si ibùgbé mímọ́ rẹ̀, àní sí ọ̀run.
"Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀
tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn,
ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá?
Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí?
Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́,
ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?"
ni Olúwa wí.
"Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì,
kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́?
Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́,
bí i ará Arabia kan nínú aginjù,
ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́
pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.
Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn,
kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò.
Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà,
ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.
Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé,
‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.
Ìwọ yóò ha máa bínú títí?
Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’
Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀
ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe."
Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, "Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀. Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i. Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè. Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi. Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́," ni Olúwa wí.
Olúwa wí fún mi pé, "Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ. Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá:
" ‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí.
‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́,
nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí.
Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé.
Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ,
ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ,
ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì
lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀,
ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’ "
ni Olúwa wí.
"Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́," ni Olúwa wí, "nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni. Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà," ni Olúwa wí, "àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa.’ Kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́. Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.
"Èmi fúnra mi sọ wí pé,
" ‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó,
kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin
kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’
Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’
o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀,
bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi. Ìwọ ilé Israẹli,"
ni Olúwa wí.
A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga,
ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli,
nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po,
wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.
"Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,
Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn."
"Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ
nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.
Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè
kéékèèké àti àwọn òkè gíga,
nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run
wa ni ìgbàlà Israẹli wà.
Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti
jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run,
ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn,
ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa,
kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀.
A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa,
àwa àti àwọn baba wa,
láti ìgbà èwe wa títí di òní
a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa."