Publicidade

Paz

Por Bíblia Online

A paz é um dos frutos do Espírito e uma promessa central de Jesus: 'Deixo-vos a paz, a minha paz vos dou.' A Bíblia nos chama a buscar, cultivar e viver na paz de Deus.

A paz de Cristo

Jesus é o Príncipe da Paz. Antes de partir, prometeu aos discípulos uma paz que o mundo não pode dar nem tirar — paz sobrenatural em meio às tribulações.

Àlàáfíà ni mo fi sílẹ fún yín pé, àlàáfíà mi ni mo fi fún yin, kì í ṣe bí ayé ti fi fún ni. Ẹ má ṣe jẹ kí ọkàn yín dàrú, ẹ má sì jẹ kí ó wárìrì.

Àlàáfíà ni mo fi sílẹ fún yín pé, àlàáfíà mi ni mo fi fún yin, kì í ṣe bí ayé ti fi fún ni. Ẹ má ṣe jẹ kí ọkàn yín dàrú, ẹ má sì jẹ kí ó wárìrì.

"Nǹkan wọnyí ni mo ti sọ fún yín tẹlẹ, kí ẹyin kí ó lè ní àlàáfíà nínú mi. Nínú ayé, ẹyin ó ní ìpọnjú; ṣùgbọn ẹ tújúká; mo ti ṣẹgun ayé."

"Nǹkan wọnyí ni mo ti sọ fún yín tẹlẹ, kí ẹyin kí ó lè ní àlàáfíà nínú mi. Nínú ayé, ẹyin ó ní ìpọnjú; ṣùgbọn ẹ tújúká; mo ti ṣẹgun ayé."

Nítorí a bí ọmọ kan fún wa,

a fi ọmọkùnrin kan fún wa,

ìjọba yóò sì wà ní èjìká rẹ.

A ó sì máa pè é ní

Ìyanu Olùdámọràn, Ọlọrun Alágbára,

Baba ayérayé, Ọmọ ọba aládé Àlàáfíà.

Bí wọn sì ti ń sọ nǹkan wọnyí Jesu tìkára rẹ dúró láàrín wọn, ó sì wí fún wọn pé, "Àlàáfíà fún yín."

Paz com Deus

Justificados pela fé, temos paz com Deus por meio de Cristo. Ele é a nossa paz, que derrubou a barreira e nos reconciliou.

Nítorí náà, níwọn ìgbà tí a ti dá wa láre nípa ìgbàgbọ, àwa ní àlàáfíà lọdọ Ọlọrun nípasẹ Olúwa wa Jesu Kristi.

Nítorí òun ni àlàáfíà wa, ẹni tí o ti ṣe méjèèjì ni ọkan, tí ó sì ti wó ògiri ìkélé ti ìkórìíra èyí tí ń bẹ láàrín yín. Ó sì ti fi òpin sí ọtá náà nínú ara rẹ, àní sí òfin àti àṣẹ wọn-ọn-nì tí ń bẹ nínú ìlànà, kí ó lè sọ àwọn méjèèjì di ẹni tuntun kan nínú ara rẹ, kí ó sì ṣe ìlàjà

Àti nípasẹ rẹ láti bá ohun gbogbo làjà àwọn nǹkan tí ń bẹ láyé àti èyí tí ń bẹ ní ọrun, nípa mímú àlàáfíà wá nípasẹ ẹjẹ rẹ, tí a ta sílẹ lórí igi àgbélébùú.

Sí gbogbo àwọn àyànfẹ Ọlọrun tí ó wà ní Romu tí a ti pè láti jẹ ènìyàn mímọ:

Oore-ọfẹ àti àlàáfíà fún yín láti ọdọ Ọlọrun Baba wa àti láti ọdọ Olúwa wa Jesu Kristi.

Oore-ọfẹ àti àlàáfíà fún yín láti ọdọ Ọlọrun Baba wa àti Olúwa wa tí í ṣe Jesu Kristi.

Oore-ọfẹ sí yín àti àlàáfíà láti ọdọ Ọlọrun Baba wá àti Jesu Kristi Olúwa,

A paz que excede o entendimento

A paz de Deus, que excede todo entendimento, guarda nosso coração e mente. Ela vem da confiança no Senhor e da entrega total a Ele.

Ẹ má ṣe ṣe àníyàn ohunkóhun; ṣùgbọn nínú ohun gbogbo, nípa àdúrà àti ẹbẹ pẹlú ìdúpẹ, ẹ máa fi ìbéèrè yín hàn fún Ọlọrun. Àti àlàáfíà Ọlọrun, tí ó ju ìmòye gbogbo lọ, yóò pa ọkàn àti èrò yín mọ nínú Kristi Jesu.

Àwọn nǹkan tí ẹyin ti kọ, tí ẹyin sì ti gbà, tí ẹyin sì ti gbọ, tí ẹyin sì ti rí lọwọ mi, ẹ máa ṣe wọn: Ọlọrun àlàáfíà yóò sì wà pẹlú yín.

Àwọn nǹkan tí ẹyin ti kọ, tí ẹyin sì ti gbà, tí ẹyin sì ti gbọ, tí ẹyin sì ti rí lọwọ mi, ẹ máa ṣe wọn: Ọlọrun àlàáfíà yóò sì wà pẹlú yín.

Ìwọ yóò pa á mọ ní àlàáfíà pípé

ọkàn ẹni tí ó dúró ṣinṣin,

nítorí ó gbẹkẹlé ọ.

Ìwọ yóò pa á mọ ní àlàáfíà pípé

ọkàn ẹni tí ó dúró ṣinṣin,

nítorí ó gbẹkẹlé ọ.

Ẹ sì jẹ kí àlàáfíà Ọlọrun kí ó máa ṣe àkóso ọkàn yín, sínú èyí tí a pè yín pẹlú nínú ara kan; kí ẹ sì máa dúpẹ.

Ẹ sì jẹ kí àlàáfíà Ọlọrun kí ó máa ṣe àkóso ọkàn yín, sínú èyí tí a pè yín pẹlú nínú ara kan; kí ẹ sì máa dúpẹ.

Promotores da paz

Bem-aventurados os pacificadores, porque serão chamados filhos de Deus. A Escritura nos chama a buscar e promover a paz em todos os relacionamentos.

Alábùkún fún ni àwọn onílàjà,

nítorí ọmọ Ọlọrun ni a ó máa pè wọn.

Alábùkún fún ni àwọn onílàjà,

nítorí ọmọ Ọlọrun ni a ó máa pè wọn.

Bí ó bá sé é ṣe, bí ó ti wà ní ipa tiyín, ẹ má wà ní àlàáfíà pẹlú gbogbo ènìyàn.

Nítorí náà, ẹ jẹ kí a ṣa gbogbo ipá wa láti máa lépa àlàáfíà, àti ohun tí àwa yóò fi gbé ara wa ró.

Nítorí ìjọba ọrun kì í ṣe jíjẹ àti mímu, bí kò ṣe nípa ti òdodo, àlàáfíà àti ayọ nínú Ẹmí Mímọ,

Ẹ máa lépa àlàáfíà pẹlú ènìyàn gbogbo, àti ìwà mímọ, láìsí èyí yìí kò sí ẹni tí yóò rí Olúwa.

Ẹ máa lépa àlàáfíà pẹlú ènìyàn gbogbo, àti ìwà mímọ, láìsí èyí yìí kò sí ẹni tí yóò rí Olúwa.

Nítorí,

"Ẹni tí yóò bá fẹ ìyè,

ti yóò sì rí ọjọ rere,

kí o pa ahọn rẹ mọ kúrò nínú ibi,

àti ètè rẹ mọ kúrò nínú sísọ ọrọ ẹtàn.

Kí ó yà kúrò nínú ibi, kí ó sì máa ṣe rere;

kí ó máa wá àlàáfíà, kí ó sì máa lépa rẹ.

Kí ó yà kúrò nínú ibi, kí ó sì máa ṣe rere;

kí ó máa wá àlàáfíà, kí ó sì máa lépa rẹ.

Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere;

wá àlàáfíà, kí o sì lépa rẹ.

Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere;

wá àlàáfíà, kí o sì lépa rẹ.

O fruto da paz

A sabedoria que vem do alto é pacífica. O fruto da justiça se semeia em paz por aqueles que cultivam a paz com mansidão.

Àwọn tí ó ń ṣiṣẹ àlàáfíà a sì máa gbin èso àlàáfíà ní àlàáfíà.

Àwọn tí ó ń ṣiṣẹ àlàáfíà a sì máa gbin èso àlàáfíà ní àlàáfíà.

Ṣùgbọn ọgbọn tí ó ti òkè wá jẹ mímọ ní àkọkọ, ti àlàáfíà, àti ti ìrẹlẹ, kì í sì í ṣòro láti bẹ, ó kún fún àánú àti fún èso rere, kì í ṣe ojúsàájú, a sì máa sọ òtítọ.

Ṣùgbọn èso ti Ẹmí ni ìfẹ, ayọ, àlàáfíà, ìpamọra, ìwà pẹlẹ, ìṣoore, ìgbàgbọ,

Èso òdodo náà yóò sì jẹ àlàáfíà;

àbájáde òdodo yóò sì jẹ ìdákẹ jẹẹ àti ìgbẹkẹlé títí láé.

Gbogbo ìbáwí kò dàbí ohun ayọ nísinsin yìí bí kò ṣe ìbànújẹ; ṣùgbọn níkẹyìn yóò so èso àlàáfíà fún àwọn tí a tọ nípa rẹ, àní èso òdodo.

Paz interior e descanso

Aquietai-vos e sabei que Eu sou Deus. A paz do Senhor acalma tempestades, silencia medos e sustenta a alma em todo tempo.

Ẹ dúró jẹẹ, kí ẹ sì mọ pé èmi ní Ọlọrun.

A ó gbé mi ga nínú àwọn orílẹ-èdè,

a ó gbé mi ga ní ayé.

Èmi yóò dùbúlẹ, èmi ó sì sùn ní àlàáfíà,

nítorí ìwọ nìkan, Olúwa,

ni o mú mi gbé láìléwu.

Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ;

bùkún àwọn ènìyàn rẹ pẹlú àlàáfíà.

Ṣùgbọn àwọn ọlọkàn tútù ni yóò jogún ilẹ náà,

wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọpọlọpọ àlàáfíà.

Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin;

nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.

Àlàáfíà púpọ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ sí òfin rẹ,

kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ.

Àlàáfíà púpọ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ sí òfin rẹ,

kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ.

Ènìyàn àlàáfíà ni mí;

ṣùgbọn nígbà tí mo bá sọrọ, ogun ni dúró fun wọn.

Ó dìde, ó bá ìjì líle náà wí, ó sì wí fún òkun pé, "Dákẹ! Jẹẹ!" Ìjì náà sì dá, ìparọrọ ńlá sì wà.

Jesu sì wí fún un pé, "Ọmọbìnrin, ìgbàgbọ rẹ mú ọ láradá. Máa lọ ní àlàáfíà, ìwọ sì ti sàn nínú ààrùn rẹ."

"Iyọ dára, ṣùgbọn tí ó bá sọ adùn rẹ nù, báwo ni ẹ ṣè lè padà mú un dùn? Ẹ ni iyọ nínú ara yín, ki ẹ sì máa gbé ní àlàáfíà pẹlú ara yín."

Anunciadores da paz

Como são formosos os pés dos que anunciam boas novas de paz! O evangelho é a mensagem de paz para todos os povos.

Wọn ó ha sì ti ṣe wàásù, bí kò ṣe pé a rán wọn? Gẹgẹ bí a ti kọ ọ pé, "Ẹsẹ àwọn tí ń wàásù ìyìnrere àlàáfíà ti dára tó, àwọn tí ń wàásù ìròyìn ayọ ohun rere!"

Báwo ni ó ṣe dára tó lórí òkè

ẹsẹ àwọn tí ó mú ìyìnrere ayọ wá,

tí wọn kéde àlàáfíà,

tí ó mú ìyìnrere wá,

tí ó kéde ìgbàlà,

tí ó sọ fún Sioni pé,

"Ọlọrun rẹ ń jẹ ọba!"

"Ògo ni fún Ọlọrun lókè ọrun,

àti ní ayé àlàáfíà, ìfẹ inú rere sí ènìyàn."

wí pé, "Olùbùkún ni ọba tí ó ń bọ wá ní orúkọ Olúwa!"

"Àlàáfíà ní ọrun, àti ògo ni òkè ọrun!"

Wò ó, lórí àwọn òkè,

àwọn ẹsẹ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ wá,

ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà.

Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ,

kí ó sì san àwọn ẹjẹ rẹ.

Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ mọ;

wọn yóò sì parun pátápátá.

Tí ẹ sì ti fi ìmúra ìyìnrere àlàáfíà wọ ẹsẹ yín ní bàtà.

O Deus da paz

Que o Deus da paz esteja com todos vocês. Ele nos santifica por completo e nos guarda irrepreensíveis para a vinda do Senhor.

Kí Ọlọrun àlàáfíà wà pẹlú gbogbo yín. Àmín.

Ǹjẹ kí Olúwa àlàáfíà, fúnra rẹ máa fún yín ní àlàáfíà nígbà gbogbo. Kí Olúwa kí ó wà pẹlú gbogbo yín.

Ǹjẹ Ọlọrun àlàáfíà, ẹni tí o tún mu olùṣọ-àgùntàn ńlá ti àwọn àgùntàn, ti inú òkú wá, nípa ẹjẹ májẹmú ayérayé, àní Olúwa wa Jesu.

Nítorí Ọlọrun kì í ṣe Ọlọrun ohun rúdurùdu, ṣùgbọn ti àlàáfíà. Gẹgẹ bí ó ti jẹ nínú gbogbo ìjọ ènìyàn mímọ.

"‘"Kí Olúwa bùkún un yín,

kí ó sì pa yín mọ.

Olúwa kí o mú ojú rẹ kí ó mọlẹ sí i yín lára.

Kí ó sì ṣàánú fún un yín.

Olúwa bojú wò yín,

kí ó sì fún un yín ní àlàáfíà."’

Nítorí mo mọ èrò tí mo rò sí yín," ni Olúwa wí, "àní èrò àlàáfíà, kì í sì ṣe fún ibi, èrò láti fún un yín ní ìgbà ìkẹyìn àti ìrètí ọjọ iwájú.

"‘Wò ó, èmi ó mú ọjá àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọpọlọpọ àlàáfíà àti òtítọ.

Gbogbo ọdọmọkùnrin rẹ ni Olúwa yóò kọ,

àlàáfíà àwọn ọmọ rẹ yóò jẹ ńlá àti púpọ.

Ẹyin yóò jáde lọ ní ayọ

a ó sì darí i yín lọ ní àlàáfíà;

òkè ńlá ńlá àti kéékèèké

yóò bú sí orin níwájú yín

àti gbogbo igi inú pápá

yóò máa pàtẹwọ.

"Kò sí àlàáfíà fún àwọn ìkà," ni Ọlọrun mi wí.

Paz, santidade e unidade

A paz exige esforço: guardar a unidade do Espírito, evitar contendas e buscar a santidade. Sem paz e santidade, ninguém verá o Senhor.

Kí ẹ sì máa làkàkà láti pa ìṣọkan Ẹmí mọ ni ìdàpọ àlàáfíà.

Kí ẹ sì máa làkàkà láti pa ìṣọkan Ẹmí mọ ni ìdàpọ àlàáfíà.

Máa sá fún ìfẹkúfẹẹ èwe, sì máa lépa òdodo, ìgbàgbọ, ìfẹ, àlàáfíà, pẹlú àwọn tí ń ké pe Olúwa láti inú ọkàn funfun wá.

Ẹ máa fi ara dà á fún ara yín, ẹ sì máa dáríjì ara yín bí ẹnikẹni bá ní ẹsùn sí ẹnìkan: bí Kristi ti dáríjì yín, gẹgẹ bẹẹ ni kí ẹyin kí ó máa ṣe pẹlú.

Nígbà tí ọnà ènìyàn bá tẹ Olúwa lọrùn,

yóò mú kí àwọn ọtá rẹ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà.

Ó sàn láti jẹ onísùúrù ju ajagun ènìyàn lọ,

ẹni tí ó pa ìbínú mọra ju ajagun ṣẹgun ìlú lọ.

Iyì ni ó jẹ fún ènìyàn láti sá fún ìjà,

ṣùgbọn gbogbo aláìgbọn a máa tètè wá ìjà.

Kí àlàáfíà àti àánú wà lórí gbogbo àwọn tí ń rìn ní ìlànà yìí, àti lórí Israẹli Ọlọrun.

Kí àánú, àlàáfíà àti ìfẹ kí ó máa jẹ tiyín ní ọpọlọpọ.

Paz e fé

O Deus da esperança nos encha de paz e alegria no crer. Quem mantém o pensamento firme no Senhor experimenta paz perfeita.

Ǹjẹ kí Ọlọrun ìrètí kí ó fi gbogbo ayọ òun àlàáfíà kún yín bí ẹyin ti gbà á gbọ, kí ẹyin kí ó lè pọ ní ìrètí nípa agbára Ẹmí Mímọ.

Nítorí èrò ti ara ikú ni; ṣùgbọn èrò ti ẹmí ni ìyè àti àlàáfíà.

Nítorí èrò ti ara ikú ni; ṣùgbọn èrò ti ẹmí ni ìyè àti àlàáfíà.

ìparun àti ìpọnjú wà lọnà wọn.

Ọnà àlàáfíà ni wọn kò sì mọ,"

"Ìbẹrù Ọlọrun kò sí níwájú wọn."

Ó sì dáhùn wí fún obìnrin náà pé, "Ìgbàgbọ rẹ gbà ọ là, máa lọ ní àlàáfíà."

"Ní ilékílé tí ẹyin bá wọ, kí ẹ kọ wí pé, ‘Àlàáfíà fún ilé yìí!’

Bí bẹẹ kọ, nígbà tí onítọhún bá sì wà ní òkèrè, òun a rán ikọ sí i, a sì bẹrẹ àdéhùn àlàáfíà.

Bí ilé náà bá sì yẹ, kí àlàáfíà yín kí ó bà sórí rẹ; ṣùgbọn bí kò bá yẹ, kí àlàáfíà yín kí ó padà sọdọ yín.

"Ẹ má ṣe rò pé mo mú àlàáfíà wá sí ayé, Èmi kò mú àlàáfíà wá bí kò ṣe idà.

Ní àkótán, ará ó dì gbòóṣe, ẹ ṣe àtúnṣe ọnà yín, ẹ tújúká, ẹ jẹ onínú kan, ẹ máa wà ní àlàáfíà, Ọlọrun ìfẹ àti ti àlàáfíà yóò wà pẹlú yín.

Láti fi ìmọlẹ fún àwọn tí ó jókòó ní

òkùnkùn àti ní òjìji ikú,

àti láti fi ẹsẹ wa lé ọnà àlàáfíà."

Ṣùgbọn ìwọ yóò tọ àwọn baba rẹ lọ ni àlàáfíà, bẹẹ ni ìwọ yóò sì di arúgbó kí a tó gbé ọ sin.

ìgbà láti ní ìfẹ àti ìgbà láti kórìíra

ìgbà fún ogun àti ìgbà fún àlàáfíà.

Ọnà àlàáfíà èyí ni wọn kò mọ;

kò sí òdodo ní ojú ọnà wọn

wọn ti sọ wọn dì ọnà kọrọkọrọ,

kò sí ẹni tí ó tọ ọnà yìí tí yóò rí àlàáfíà.

Nípa àrékérekè rẹ, yóò mú kí ẹtàn gbèrú, yóò gbé ara rẹ ga nínú ọkàn rẹ, nígbà tí wọn rò wí pé àlàáfíà dé, yóò sì pa àwọn ènìyàn run, nígbà tí wọn kò rò tẹlẹ, yóò sì lòdì sí olórí àwọn ọmọ-aládé, síbẹ, a ó pa á run ṣùgbọn kì í ṣe nípa agbára ènìyàn.

Nígbà tí àwọn agbègbè tí ó lọrọ gidigidi wà láìbẹrù ni yóò gbóguntì wọn, yóò ṣe ohun tí baba rẹ tàbí baba ńlá rẹ kò ṣe rí, yóò pín ìkógun ẹrù àti ọrọ fún àwọn ọmọ lẹyìn in rẹ. Yóò pète àti bi àwọn ìlú olódi ṣubú, ṣùgbọn fún ìgbà díẹ ni.

Nígbà tí ìpayà bá dé,

wọn yóò wá àlàáfíà, lórí asán.

Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹlẹ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí."’

"Májẹmú mi wà pẹlú rẹ, májẹmú ti ìyè àti àlàáfíà wà pẹlú rẹ; mo sì fi wọn fún un, nítorí bíbẹrù tí ó bẹrù mi, tí ẹrù orúkọ mi sì bà á.

Ṣùgbọn bí ẹyin tí i ṣe aláìgbàgbọ náà bá fẹ láti lọ, jẹ kí ó máa lọ. Arákùnrin tàbí arábìnrin náà kò sí lábẹ ìdè mọ; Ọlọrun ti pè wá láti gbé ní àlàáfíà.

Ẹṣin mìíràn tí ó pupa sì jáde, a sì fi agbára fún ẹni tí ó jókòó lórí rẹ, láti gba àlàáfíà kúrò lórí ilẹ ayé, àti pé kí wọn kí ó máa pa ara wọn, a sì fi idà ńlá kan lé e lọwọ.

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-19_11-20-24-