Publicidade

Jonas 2

Àdúrà Jona

1 Nígbà náà ni Jona gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ láti inú ẹja náà wá, 2 Ó sì wí pé:

"Nínú ìpọ́njú mi ni mo kígbe sí Olúwa,

òun sì gbọ́ ohùn mi.

Mo kígbe láti inú ipò òkú, mo pè fún ìrànwọ́,

ìwọ sì gbọ́ ohùn mi.

3 Nítorí tí ìwọ ti sọ mí sínú ibú,

ní àárín Òkun,

ìṣàn omi sì yí mi káàkiri;

gbogbo bíbì omi àti rírú omi

rékọjá lórí mi.

4 Nígbà náà ni mo wí pé,

‘A ta mí nù kúrò níwájú rẹ;

ṣùgbọ́n síbẹ̀ èmi yóò tún

máa wo ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ.’

5 Omi yí mi káàkiri, àní títí dé ọkàn;

ibú yí mi káàkiri,

a fi koríko odò wé mi lórí.

6 Èmi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ àwọn òkè ńlá;

ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ìdènà rẹ̀ yí mi ká títí:

ṣùgbọ́n ìwọ ti mú ẹ̀mí mi wá sókè láti inú ibú wá,

Olúwa Ọlọ́run mi.

7 "Nígbà tí ó rẹ ọkàn mi nínú mi,

èmi rántí rẹ, Olúwa,

àdúrà mi sì wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,

nínú tẹmpili mímọ́ rẹ.

8 "Àwọn tí ń fàmọ́ òrìṣà èké

kọ àánú ara wọn sílẹ̀.

9 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi orin ọpẹ́, rú ẹbọ sí ọ.

Èmi yóò san ẹ̀jẹ́ tí mo ti jẹ́.

‘Ìgbàlà wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.’ "

10 Olúwa sì pàṣẹ fún ẹja náà, ó sì pọ Jona sí orí ilẹ̀ gbígbẹ.

Veja também

Publicidade
Jonas
Ver todos os capítulos de Jonas
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-