30 Jesu sì dáhùn wí pé, "Kì í ṣe nítorí mi ni ohùn yìí ṣe wá, bí kò ṣe nítorí yín. 31 12.31: Jh 16.11; 2Kọ 4.4; Ef 2.2.Ní ìsinsin yìí ni ìdájọ́ ayé yìí dé: nísinsin yìí ni a ó lé aládé ayé yìí jáde. 32 12.32: Jh 3.14; 8.28.Àti èmi, bí a bá gbé mi sókè kúrò ní ayé, èmi ó fa gbogbo ènìyàn sọ́dọ̀ ara mi!"
Publicidade