Jesu fi ara han Maria Magdalene
11 Ṣùgbọ́n Maria dúró létí ibojì lóde, ó ń sọkún: bí ó ti ń sọkún, bẹ́ẹ̀ ni ó bẹ̀rẹ̀, ó sì wo inú ibojì. 12 20.12: Lk 24.4; Mt 28.5; Mk 16.5.Ó sì kíyèsi àwọn angẹli méjì aláṣọ funfun, wọ́n jókòó, ọ̀kan níhà orí àti ọ̀kan níhà ẹsẹ̀, níbi tí òkú Jesu gbé ti sùn sí.
13 20.13: Jh 20.2. Wọ́n sì wí fún un pé, "Obìnrin yìí, èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún?"
Ó sì wí fún wọn pé, "Nítorí tí wọ́n ti gbé Olúwa mi, èmi kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé tẹ́ ẹ sí." 14 20.14: Mt 28.9; Jh 21.4.Nígbà tí ó sì ti wí èyí tan, ó yípadà, ó sì rí Jesu dúró, kò sì mọ̀ pé Jesu ni.
15 Jesu wí fún un pé, "Obìnrin yìí, èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Ta ni ìwọ ń wá?"
Òun ṣe bí olùṣọ́gbà ní í ṣe, ó wí fún un pé, "Alàgbà, bí ìwọ bá ti gbé e kúrò níhìn-ín yìí, sọ ibi tí ìwọ tẹ́ ẹ sí fún mi, èmi yóò sì gbé e kúrò."
16 Jesu wí fún un pé, "Maria!"
Ó sì yípadà, ó wí fún un ní èdè Heberu pé, "Rabboni!" (èyí tí ó túmọ̀ sí "Olùkọ́").
17 20.17: Jh 20.27; Mt 28.10; Jh 7.33. Jesu wí fún un pé, "Má ṣe fi ọwọ́ kàn mí; nítorí tí èmi kò tí ì gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Baba mi. Ṣùgbọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin mi, sì wí fún wọn pé, ‘Èmi ń gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Baba mi, àti Baba yín, àti sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run mi, àti Ọlọ́run yín.’ "
18 20.18: Lk 24.10,23. Maria Magdalene wá, ó sì sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, "Òun ti rí Olúwa!" Àti pé, ó sì ti fi nǹkan wọ̀nyí fún òun.