Publicidade

Lamentações 2

1 Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni

pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀!

Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀,

láti ọ̀run sí ayé;

kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀

ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.

2 Láìní àánú ni Olúwa gbé

ibùgbé Jakọbu mì;

nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó

ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀.

Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin

lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.

3 Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké

gbogbo ìwo Israẹli.

Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò

nígbà tí àwọn ọ̀tá dé.

Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná

ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.

4 Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá;

ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra.

Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun

ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná

sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.

5 Olúwa dàbí ọ̀tá;

ó gbé Israẹli mì.

Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì

ó pa ibi gíga rẹ̀ run.

Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀

fún àwọn ọmọbìnrin Juda.

6 Ó mú ìparun bá ibi mímọ́,

ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run.

Olúwa ti mú Sioni gbàgbé

àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn;

nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run

ọba àti olórí àlùfáà.

7 Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀

ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀.

Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́

àwọn odi ààfin rẹ̀;

wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa

gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.

8 Olúwa pinnu láti fa

ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya.

Ó gbé wọn sórí òsùwọ̀n,

kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn.

Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀

wọ́n ṣòfò papọ̀.

9 Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀;

òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́.

Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,

kò sí òfin mọ́,

àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí

ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.

10 Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni

jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́;

wọ́n da eruku sí orí wọn

wọ́n sì wọ aṣọ àkísà.

Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu

ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.

11 Ojú mi kọ̀ láti sọkún,

mo ń jẹ ìrora nínú mi,

mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀

nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run,

nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú

ní òpópó ìlú.

12 Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn,

"Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?" Wò ó

bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe

ní àwọn òpópónà ìlú,

bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò

láti ọwọ́ ìyá wọn.

13 Kí ni mo le sọ fún ọ?

Pẹ̀lú kí ni mo lè fi ọ́ wé,

ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu?

Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé,

kí n lè tù ọ́ nínú,

ìwọ wúńdíá obìnrin Sioni?

Ọgbẹ́ rẹ jì bí Òkun.

Ta ni yóò wò ọ́ sàn?

14 Ìran àwọn wòlíì rẹ

jẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n;

wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn

tí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ.

Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọ

jẹ́ èké àti ìmúniṣìnà.

15 Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹ

pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí;

wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọn

sí ọmọbìnrin Jerusalẹmu:

"Èyí ha ni ìlú tí à ń pè

ní àṣepé ẹwà,

ìdùnnú gbogbo ayé?"

16 Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọn

gbòòrò sí ọ;

wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payínkeke

wọ́n wí pé, "A ti gbé e mì tán.

Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí;

tí a sì wá láti rí."

17 Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu;

ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ,

tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́.

Ó ti ṣí ọ ní ipò láì láàánú,

ó fún ọ̀tá ní ìṣẹ́gun lórí rẹ,

ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.

18 Ọkàn àwọn ènìyàn

kígbe jáde sí Olúwa.

Odi ọmọbìnrin Sioni,

jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ sàn bí odò

ní ọ̀sán àti òru;

má ṣe fi ara rẹ fún ìtura,

ojú rẹ fún ìsinmi.

19 Dìde, kígbe sókè ní àṣálẹ́,

bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀

tú ọkàn rẹ̀ jáde bí omi

níwájú Olúwa.

Gbé ọwọ́ yín sókè sí i

nítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀

tí ó ń kú lọ nítorí ebi

ní gbogbo oríta òpópó.

20 "Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó.

Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyí.

Ǹjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn,

àwọn ọmọ tí wọn ń ṣe ìtọ́jú fún?

Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíì

ní ibi mímọ́ Olúwa?

21 "Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀

sínú eruku àwọn òpópó;

àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi

ti ṣègbé nípa idà.

Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ,

Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.

22 "Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àsè,

bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi.

Ní ọjọ́ ìbínú Olúwa

kò sí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè;

àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn,

ni ọ̀tá mi parun."

Veja também

Publicidade
Lamentações
Ver todos os capítulos de Lamentações
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-