Publicidade

Lamentações 4

1 Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù,

wúrà dídára di àìdán!

Òkúta ibi mímọ́ wá túká

sí oríta gbogbo òpópó.

2 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye,

tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe

wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán

iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!

3 Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn

fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn,

ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn

bí ògòǹgò ní aginjù.

4 Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́

lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn;

àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ,

ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.

5 Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára

di òtòṣì ní òpópó.

Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀

ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.

6 Ìjìyà àwọn ènìyàn mi

tóbi ju ti Sodomu lọ,

tí a sí ní ipò ní òjijì

láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.

7 Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì,

wọ́n sì funfun ju wàrà lọ

wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa,

ìrísí wọn dàbí safire.

8 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú;

wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó.

Ara wọn hun mọ́ egungun;

ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.

9 Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn

ju àwọn tí ìyàn pa;

tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò

fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.

10 Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú

ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ

tí ó di oúnjẹ fún wọn

nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.

11 Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀;

ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde.

Ó da iná ní Sioni

tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.

12 Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́,

tàbí àwọn ènìyàn ayé,

wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ

odi ìlú Jerusalẹmu.

13 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì

àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà,

tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo

sílẹ̀ láàrín rẹ̀.

14 Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó

bí ọkùnrin tí ó fọ́jú.

Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n

tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.

15 "Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!" ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn.

"Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!"

Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé,

"Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́."

16 Olúwa ti tú wọn ká fúnra rẹ̀;

kò sí bojútó wọn mọ́.

Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́,

àti àánú fún àwọn àgbàgbà.

17 Síwájú sí i, ojú wa kùnà

fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán;

láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò

fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.

18 Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri,

àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́.

Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye

nítorí òpin wa ti dé.

19 Àwọn tí ń lé wa yára

ju idì ojú ọ̀run lọ;

wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè

wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.

20 Ẹni àmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa,

ni wọ́n fi tàkúté wọn mú.

Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀

ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.

21 Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu,

ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi.

Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú;

ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.

22 Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin;

kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́.

Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà

yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.

Veja também

Publicidade
Lamentações
Ver todos os capítulos de Lamentações
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-