Peteru sẹ́ Jesu
54 22.54-55: Mt 26.57-58; Mk 14.53-54; Jh 18.12-16. Wọ́n sì gbá a mú, wọ́n sì fà á lọ, wọ́n sì mú un wá sí ilé olórí àlùfáà. Ṣùgbọ́n Peteru tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ní òkèrè. 55 Nígbà tí wọ́n sì ti dáná láàrín àgbàlá, tí wọ́n sì jókòó pọ̀, Peteru jókòó láàrín wọn. 56 22.56-62: Mt 26.69-75; Mk 14.66-72; Jh 18.16-18,25-27.Ọmọbìnrin kan sì rí i bí ó ti jókòó níbi ìmọ́lẹ̀ iná náà, ó sì tẹjúmọ́ ọn, ó ní, "Eléyìí náà wà pẹ̀lú rẹ̀."
57 Ṣùgbọ́n, ó wí pé, "Obìnrin yìí, èmi kò mọ̀ ọ́n."
58 Kò pẹ́ lẹ́yìn náà ẹlòmíràn sì rí i, ó ní, "Ìwọ pẹ̀lú wà nínú wọn."
Ṣùgbọ́n Peteru wí pé, "Ọkùnrin yìí, èmi kọ́."
59 Ó sì tó bí i wákàtí kan síbẹ̀ ẹlòmíràn tẹnumọ́ ọn, wí pé, "Nítòótọ́ eléyìí náà wà pẹ̀lú rẹ̀: nítorí ará Galili ní í ṣe."
60 Ṣùgbọ́n Peteru wí pé, "Ọkùnrin yìí, èmi kò mọ ohun tí ìwọ ń wí!" Lójúkan náà, bí ó tí ń wí lẹ́nu, àkùkọ kọ! 61 22.61: Lk 7.13; 22.34.Olúwa sì yípadà, ó wo Peteru. Peteru sì rántí ọ̀rọ̀ Olúwa, bí ó ti wí fún un pé, "Kí àkùkọ tó kọ, ìwọ ó sẹ́ mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta." 62 Peteru sì bọ́ sí òde, ó sọkún kíkorò.