Jesu bá rírú omi okun wí
22 8.22-25: Mt 8.23-27; Mk 4.35-41; 6.47-52; Jh 6.16-21. Ní ọjọ́ kan, ó sì wọ ọkọ̀ ojú omi kan lọ òun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. O sì wí fún wọn pé, "Ẹ jẹ́ kí a rékọjá lọ sí ìhà kejì adágún." Wọ́n sì ṣíkọ̀ láti lọ. 23 Bí wọ́n sì ti ń lọ, ó sùn; ìjì ńlá sì dé, ó ń fẹ́ lójú adágún; omi si wọ inú ọkọ, wọ́n sì wà nínú ewu.
24 8.24: Lk 5.5; 8.45; 9.33,49; 17.13. Wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá wọ́n sì jí i, wí pé, "Olùkọ́, Olùkọ́, àwa yóò ṣègbé!"
Nígbà náà ni ó dìde, ó sì bá ìjì líle àti ríru omi wí; wọ́n sì dúró, ìdákẹ́rọ́rọ́ sì dé. 25 Ó sì wí fún wọn pé, "Ìgbàgbọ́ yín dà?"
Bí ẹ̀rù ti ń ba gbogbo wọn, tí hà sì ń ṣe wọ́n, wọ́n ń bi ara wọn pé, "Irú ọkùnrin wo ni èyí, nítorí ó bá ìjì líle àti ríru omi wí, wọ́n sì gbọ́ tirẹ̀?"