Publicidade

Cânticos 5

Olùfẹ́

1 Mo ti dé inú ọgbà mi, arábìnrin mi, ìyàwó mi;

mo ti kó òjìá pẹ̀lú òórùn dídùn mi jọ.

Mo ti jẹ afárá mi pẹ̀lú oyin mi;

mo ti mu ọtí wáìnì mi pẹ̀lú wàrà mi.

Ọ̀rẹ́

Ẹ jẹ, ẹ̀yin ọ̀rẹ́, ẹ mu,

àní ẹ mu àmuyó, ẹ̀yin olùfẹ́.

Olólùfẹ́

2 Mo ti sùn ṣùgbọ́n ọkàn mi jí.

Gbọ́! Olólùfẹ́ mi ń kan ìlẹ̀kùn.

"Ṣí i fún mi, arábìnrin mi, olùfẹ́ mi,

àdàbà mi, aláìlábàwọ́n mi,

orí mi kún fún omi ìrì,

irun mi kún fún òtútù òru."

3 Mo ti bọ́ aṣọ ìgúnwà mi

ṣé èmi gbọdọ̀ tún gbé e wọ̀?

Mo ti wẹ ẹsẹ̀ mi

ṣé èmi gbọdọ̀ tún tì í bọ eruku?

4 Olùfẹ́ mi na ọwọ́ rẹ̀ láti inú ihò ìlẹ̀kùn

inú mi sì yọ́ sí i.

5 Èmi dìde láti ṣílẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,

òjìá bẹ̀rẹ̀ sí í kán ní ọwọ́ mi,

òjìá olóòórùn ń ti ara ìka mi ń sàn

sí orí ìdìmú ìlẹ̀kùn.

6 Èmi ṣí ìlẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,

ṣùgbọ́n olùfẹ́ mi ti kúrò, ó ti lọ

ọkàn mi gbọgbẹ́ fún lílọ rẹ̀.

Mo wá a kiri ṣùgbọ́n, n kò rí i.

Mo pè é ṣùgbọ́n, kò dáhùn.

7 Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlú rí mi

bí wọ́n ti ṣe ń rìn yí ìlú ká.

Wọ́n nà mí, wọ́n sá mi lọ́gbẹ́;

wọ́n gba ìborùn mi lọ́wọ́ mi.

Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ odi!

8 Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu, mo bẹ̀ yín

bí ẹ̀yin bá rí olùfẹ́ mi,

kí ni ẹ̀yin yóò wí fún un?

Ẹ wí fún un pé àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mi.

Ọ̀rẹ́

9 Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ,

ìwọ arẹwà jùlọ láàrín àwọn obìnrin?

Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ

tí ìwọ fi ń fi wá bú bẹ́ẹ̀?

Olólùfẹ́

10 Olùfẹ́ mi ní ìtànṣán ó sì pọ́n

ó ní ọlá ju ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) lọ.

11 Orí rẹ̀ rí bí i wúrà tí ó dára jùlọ

ìdì irun rẹ̀ rí bí i imọ̀ ọ̀pẹ

ó sì dúdú bí i ẹyẹ ìwò.

12 Ojú rẹ̀ rí bí i ti àdàbà

ní ẹ̀bá odò tí ń sàn,

tí a fi wàrà wẹ̀,

tí ó jì, tí ó sì dákẹ́ rọ́rọ́.

13 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ rí bí ibùsùn tùràrí

tí ó sun òórùn tùràrí dídùn

Ètè rẹ̀ rí bí i ìtànná lílì

ó ń kán òjìá olóòórùn dídùn.

14 Apá rẹ̀ rí bí i ọ̀pá wúrà,

tí a to ohun ọ̀ṣọ́ sí yíká.

Ara rẹ̀ rí bí i eyín erin dídán

tí a fi safire ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.

15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ rí bí i òpó mabu

tí a gbé ka ihò ìtẹ̀bọ̀ wúrà dáradára.

Ìrísí rẹ̀ rí bí igi kedari Lebanoni,

tí dídára rẹ̀ kò ní ẹgbẹ́.

16 Ẹnu rẹ̀ jẹ́ adùn fún ara rẹ̀

ó wu ni pátápátá.

Háà! Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu.

Èyí ni olùfẹ́ mi, èyí sì ni ọ̀rẹ́ mi.

Veja também

Publicidade
Cânticos
Ver todos os capítulos de Cânticos
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-