Publicidade

Isaías 12

Orin ìyìn

1 Ní ọjọ́ náà ni ìwọ ó wí pé,

"Èmi ó yìn ọ́, Olúwa.

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ò ti bínú sí mi

ìbínú rẹ ti yí kúrò níbẹ̀

ìwọ sì ti tù mí nínú.

2 Nítòótọ́ Ọlọ́run ni ìgbàlà mi,

èmi yóò gbẹ́kẹ̀lé e èmi kì yóò bẹ̀rù.

Olúwa, Olúwa náà ni agbára à mi àti orin ìn mi,

òun ti di ìgbàlà mi."

3 Pẹ̀lú ayọ̀ ni ìwọ yóò máa pọn omi

láti inú kànga ìgbàlà.

4 Ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò wí pé,

"Fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀,

jẹ́ kí ó di mí mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,

ohun tí ó ti ṣe

kí o sì kéde pé a ti gbé

orúkọ rẹ̀ ga.

5 Kọ orin sí Olúwa, nítorí ó ti ṣe ohun tí ó lógo,

jẹ́ kí èyí di mí mọ̀ fún gbogbo ayé.

6 Kígbe sókè kí o sì kọrin fún ayọ̀, ẹ̀yin ènìyàn Sioni,

nítorí títóbi ni ẹni mímọ́ kan ṣoṣo

ti Israẹli láàrín yín."

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-