Publicidade

Isaías 45

1 "Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀,

sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú

láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀

àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn,

láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀

tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.

2 Èmi yóò lọ síwájú rẹ,

Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ

Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ

èmi ó sì gé ọ̀pá irin.

3 Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn,

ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin,

tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa,

Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.

4 Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi

àti Israẹli ẹni tí mo yàn,

Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ,

mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.

5 Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn;

yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan,

Èmi yóò fún ọ ní okun,

bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,

6 tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn

títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀

kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi.

Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.

7 Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn,

Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù;

Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.

8 "Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀;

jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀.

Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada,

jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè,

jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀;

Èmi Olúwa ni ó ti dá a.

9 "Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà,

ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀.

Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé:

‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’

Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé,

‘Òun kò ní ọwọ́?’

10 Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé,

‘Kí ni o bí?’

tàbí sí ìyá rẹ̀,

‘Kí ni ìwọ ti bí?’

11 "Ohun tí Olúwa wí nìyìí,

Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀.

Nípa ohun tí ó ń bọ̀,

ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi,

tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?

12 Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé

tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀.

Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run;

mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.

13 Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi.

Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.

Òun yóò tún ìlú mi kọ́

yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀,

ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan,

ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí."

14 Ohun tí Olúwa wí nìyìí:

"Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi,

àti àwọn Sabeani—

wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ

wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ;

wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn,

wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́.

Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀,

wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé,

‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn;

kò sí ọlọ́run mìíràn.’ "

15 Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́,

Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,

16 Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì

wọn yóò sì kan àbùkù;

gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.

17 Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa

pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé;

a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín,

títí ayé àìnípẹ̀kun.

18 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí,

ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run,

Òun ni Ọlọ́run;

ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé,

Òun ló ṣe é;

Òun kò dá a láti wà lófo,

ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀,

Òun wí pé:

"Èmi ni Olúwa,

kò sì ṣí ẹlòmíràn.

19 Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin,

láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn,

Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé,

‘Ẹ wá mi lórí asán.’

Èmi Olúwa sọ òtítọ́,

Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.

20 "Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá;

ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá.

Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri,

tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.

21 Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá,

jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀.

Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́,

ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe?

Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa?

Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi,

Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà;

kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.

22 "Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là,

ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé;

nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.

23 Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra,

ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi,

ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́.

Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀;

nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.

24 Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni

òdodo àti agbára wà.’ "

Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí;

yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.

25 Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli

ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_06-50-08-