Publicidade

Isaías 31

Ègbé ni fún àwọn tí o gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti

1 Ègbé ni fún àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí

Ejibiti fún ìrànlọ́wọ́,

tí wọn gbẹ́kẹ̀lé ẹṣin

tí wọ́n fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́-ẹṣin wọn

àti agbára ńlá àwọn ẹlẹ́ṣin wọn,

ṣùgbọ́n tiwọn kò bojú wo Ẹni Mímọ́ Israẹli n nì,

tàbí kí wọn wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Olúwa.

2 Síbẹ̀síbẹ̀ òun pẹ̀lú jẹ́ ọlọ́gbọ́n ó sì lè mú ìparun wá;

òun kì í kó ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ.

Òun yóò dìde sí ilé àwọn ìkà,

àti sí àwọn tí ń ṣe ìrànlọ́wọ́ fún aṣebi.

3 Ṣùgbọ́n ènìyàn lásán ni àwọn ará Ejibiti

wọn kì í ṣe Ọlọ́run;

ẹran-ara ni àwọn ẹṣin wọn, kì í ṣe ẹ̀mí.

Nígbà tí Olúwa bá na ọwọ́ rẹ̀ jáde,

ẹni náà tí ó ń ṣèrànwọ́ yóò kọsẹ̀,

ẹni náà tí à ń ràn lọ́wọ́ yóò ṣubú;

àwọn méjèèjì yóò sì jùmọ̀ parun.

4 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi:

"Gẹ́gẹ́ bí i kìnnìún ti í ké

àní kìnnìún ńlá lórí ẹran ọdẹ rẹ̀

bí a tilẹ̀ rí ẹgbẹ́ àwọn olùṣọ́-àgùntàn

tí a sì pè wọ́n papọ̀ láti kojú rẹ̀,

ẹ̀rù kò lè bà á pẹ̀lú igbe wọn

akitiyan wọn kò sì lè dí i lọ́wọ́

bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò sọ̀kalẹ̀ wá

láti jagun lórí òkè Sioni àti lórí ibi gíga rẹ̀.

5 Gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹyẹ ti ń rábàbà lókè

Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bo Jerusalẹmu,

Òun yóò dáàbò bò ó, yóò sì tú u sílẹ̀

Òun yóò ré e kọjá yóò sì gbà á sílẹ̀."

6 Ẹ padà sọ́dọ̀ ẹni tí ẹ ti ṣọ̀tẹ̀ sí gidigidi, ẹ̀yin ọmọ Israẹli.

7 Nítorí ní ọjọ́ náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò kọ àwọn ère fàdákà àti wúrà tí ọwọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín ti ṣe.

8 "Asiria yóò ṣubú lọ́wọ́ idà kan tí kò ti ọwọ́ ènìyàn wá;

idà tí kì í ṣe ti ẹ̀dá alààyè ni yóò pa wọ́n.

Wọn yóò sì sá níwájú idà náà

àti àwọn ọmọkùnrin wọn ni a ó fún ní iṣẹ́ ipá ṣe.

9 Àpáta rẹ yóò kọjá lọ fún ẹ̀rù;

àwọn olórí rẹ yóò bẹ̀rù asia náà,"

ni Olúwa wí,

ẹni tí iná rẹ̀ ń bẹ ní Sioni,

ẹni tí ìléru rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-