Publicidade

Isaías 61

Ọdún ojúrere Olúwa

1 Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi

nítorí Olúwa ti fi àmì òróró yàn mí

láti wàásù ìyìnrere fún àwọn tálákà.

Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́

láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn

àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,

2 láti kéde ọdún ojúrere Olúwa

àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa,

láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,

3 àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni

láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú,

òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀,

àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn.

A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo,

irúgbìn Olúwa

láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.

4 Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́

wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò;

wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà

tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.

5 Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ;

àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.

6 A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa,

a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa.

Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè

àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.

7 Dípò àbùkù wọn

àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì,

àti dípò àbùkù wọn

wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn;

bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn,

ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.

8 "Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo;

mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀.

Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn

èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.

9 A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè

àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn.

Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé

wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún."

10 Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa;

ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi.

Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà

ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo;

gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà,

àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.

11 Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde

àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà,

bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn

kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-