Publicidade

Isaías 62

Orúkọ Sioni tuntun

1 Nítorí Sioni èmi kì yóò dákẹ́,

nítorí i Jerusalẹmu èmi kì yóò sinmi ẹnu,

títí tí òdodo rẹ̀ yóò fi tàn bí òwúrọ̀,

àti ìgbàlà rẹ̀ bí i fìtílà tí ń jó geere.

2 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò rí òdodo rẹ,

àti gbogbo ọba ògo rẹ

a ó sì máa pè ọ́ ní orúkọ mìíràn

èyí tí ẹnu Olúwa yóò fi fún un.

3 Ìwọ yóò sì jẹ́ adé dídán ní ọwọ́ Olúwa,

adé ọba ní ọwọ́ Ọlọ́run rẹ.

4 Wọn kì yóò pè ọ́ ní ìkọ̀sílẹ̀ mọ́

tàbí kí wọ́n pe ilẹ̀ rẹ ní ahoro.

Ṣùgbọ́n a ó máa pè ọ́ ní Hẹfsiba,

àti ilẹ̀ rẹ ní Beula;

nítorí Olúwa yóò yọ́nú sí ọ

àti ilẹ̀ rẹ ni a ó gbé níyàwó.

5 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́mọkùnrin tí í gbé ọ̀dọ́mọbìnrin níyàwó,

bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin rẹ yóò gbé ọ níyàwó

Gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ṣe é yọ̀ lórí ìyàwó rẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run rẹ yóò yọ̀ lórí rẹ.

6 Èmi ti fi olùṣọ́ ránṣẹ́ sórí odi rẹ ìwọ Jerusalẹmu;

wọn kì yóò lè dákẹ́ tọ̀sán tòru.

Ẹ̀yin tí ń ké pe Olúwa,

ẹ má ṣe fúnra yín ní ìsinmi,

7 àti kí ẹ má ṣe fún òun pẹ̀lú ní ìsinmi

títí tí yóò fi fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀

tí yóò sì fi ṣe ìyìn orí ilẹ̀ ayé.

8 Olúwa ti búra pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀

àti nípa agbára apá rẹ:

"Èmi kì yóò jẹ́ kí ìyẹ̀fun rẹ

di oúnjẹ fún ọ̀tá rẹ

bẹ́ẹ̀ ni àwọn àjèjì kì yóò mu wáìnì

tuntun rẹ mọ́

èyí tí ìwọ ti ṣe làálàá fún;

9 ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá kóórè rẹ̀ ni yóò jẹ ẹ́,

tí wọn ó sì yin Olúwa,

àti àwọn tí wọ́n bá kó àjàrà jọ ni wọn ó mú un,

nínú àgbàlá ilé mímọ́ mi."

10 Ẹ kọjá, ẹ kọjá ní ẹnu ibodè náà!

Ẹ tún ọ̀nà ṣe fún àwọn ènìyàn.

Ẹ mọ ọ́n sókè, ṣe ojú ọ̀nà òpópó!

Ẹ ṣa òkúta kúrò.

Ẹ gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè.

11 Olúwa ti ṣe ìkéde

títí dé òpin ilẹ̀ ayé:

"Ẹ sọ fún ọmọbìnrin Sioni pé,

‘Kíyèsi i, Olùgbàlà rẹ ń bọ̀!

Kíyèsi i, èrè ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀,

àti ẹ̀san rẹ̀ pẹ̀lú n tẹ̀lé e lẹ́yìn.’ "

12 A ó sì pè wọ́n ní Ènìyàn Mímọ́,

ẹni ìràpadà Olúwa;

a ó sì máa pè ọ́ ní ìwákiri,

ìlú tí a kì yóò kọ̀sílẹ̀.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_18-40-07-