Publicidade

Salmos 112

1 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run,

tí ó ní inú dídùn ńlá sí àwọn òfin rẹ̀.

2 Irú-ọmọ rẹ̀ yóò jẹ́ alágbára ní ayé:

ìran àwọn olóòtítọ́ ni a ó bùkún fún.

3 Ọlá àti ọrọ̀ yóò wà nínú ilé rẹ̀;

òdodo rẹ̀ sì dúró láé.

4 Fún olóòótọ́ ni ìmọ́lẹ̀ yóò tàn fún ní òkùnkùn:

olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú àti òdodo.

5 Ènìyàn rere fi ojúrere hàn,

a sì wínni;

ìmòye ni yóò máa fi la ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀.

6 Dájúdájú a kì yóò le yí ní ipò padà láéláé:

olódodo ni a ó máa ṣe ìrántí rẹ láéláé.

7 Òun kì yóò béèrè ìyìn búburú:

ọkàn rẹ̀ ti dúró, ó ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa.

8 Ó ti mú ọkàn rẹ̀ gbilẹ̀, ẹ̀rù kí yóò bà á,

títí yóò fi rí ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.

9 Ó ti pín ká, ó ti fi fún àwọn olùpọ́njú,

nítorí òdodo rẹ̀ dúró láé;

ìwo rẹ̀ ní a ó gbé sókè pẹ̀lú ọlá.

10 Ènìyàn búburú yóò ri, inú wọn yóò sì bàjẹ́,

yóò sì pa eyín keke, yó sì yọ dànù:

èròǹgbà ọkàn ènìyàn búburú ni yóò ṣègbé.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-