Publicidade

Salmos 114

1 Nígbà tí Israẹli jáde ní Ejibiti,

ilé Jakọbu láti inú ènìyàn àjèjì èdè

2 Juda wà ní ibi mímọ́,

Israẹli wà ní ìjọba.

3 Òkun sì rí i, ó sì wárìrì:

Jordani sì padà sẹ́yìn.

4 Àwọn òkè ńlá ń fò bí àgbò àti

òkè kéékèèké bí ọ̀dọ́-àgùntàn.

5 Kí ni ó ṣe ọ́, ìwọ Òkun, tí ìwọ fi wárìrì?

Ìwọ Jordani, tí ìwọ fi padà sẹ́yìn?

6 Ẹ̀yin òkè ńlá kí ló dé ti ẹ fi ń fò bí àgbò,

àti ẹ̀yin òkè kéékèèké bí ọ̀dọ́-àgùntàn?

7 Wárìrì, ìwọ ilẹ̀, níwájú Olúwa;

ní iwájú Ọlọ́run Jakọbu

8 tí ó sọ àpáta di adágún omi,

àti òkúta-ìbọn di orísun omi.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_18-40-07-