Publicidade

Salmos 19

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

1 Àwọn ọ̀run ń sọ nípa ti ògo Ọlọ́run;

àwọsánmọ̀ ń sọ nípa ti iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.

2 Wọ́n ń fọhùn ní ọjọ́ dé ọjọ́;

wọ́n ń fi ìmọ̀ hàn ní alẹ́ dé alẹ́.

3 Kò sí ohùn tàbí èdè

níbi tí a kò gbé gbọ́ ìró wọn.

4 Ohùn wọn jáde lọ sí gbogbo orílẹ̀ ayé,

ọ̀rọ̀ wọn títí dé òpin ilẹ̀ ayé.

Ó ti kọ́ àgọ́ fún oòrùn nínú àwọn ọ̀run.

5 Tí ó dàbí ọkọ ìyàwó tí ó ń jáde ti yàrá rẹ̀ wá,

òun yọ bí alágbára ọkùnrin tí ó ń sáré ìje.

6 Ìjáde lọ rẹ̀ ni láti òpin ọ̀run wá

àti àyíká rẹ̀ sì dé ìpínlẹ̀ rẹ̀;

kò sì sí ohun tí ó pamọ́ kúrò nínú oore rẹ̀.

7 Pípé ni òfin Olúwa,

ó ń yí ọkàn padà.

Ẹ̀rí Olúwa dánilójú,

ó sọ òpè di ọlọ́gbọ́n.

8 Ìlànà Olúwa tọ̀nà,

ó ń fi ayọ̀ fún ọkàn.

Àṣẹ Olúwa ni mímọ́,

ó ń fi ìmọ́lẹ̀ fún ojú.

9 Ìbẹ̀rù Olúwa mọ́,

ó ń faradà títí láéláé.

Ìdájọ́ Olúwa dájú

òdodo ni gbogbo wọn.

10 Wọn ṣọ̀wọ́n ju wúrà lọ,

ju wúrà tí o dára jùlọ,

wọ́n dùn ju oyin lọ,

àti ju afárá oyin lọ.

11 Nípa wọn ni a ti ṣí ìránṣẹ́ rẹ̀ létí;

nípa pípa wọ́n mọ́, èrè púpọ̀ ń bẹ.

12 Ta ni ó lè mọ àṣìṣe rẹ̀?

Dáríjì mí nínú àṣìṣe mi tí ó pamọ́.

13 Wẹ ìránṣẹ́ rẹ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀ọ́n-mọ̀-dá;

má ṣe jẹ kí wọn kí ó jẹ ọba lórí mi.

Nígbà náà ní èmi yóò dúró ṣinṣin,

èmi yóò sì ṣe aláìlẹ́bi kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.

14 Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi àti àṣàrò ọkàn mi

kí ó jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú rẹ,

Ìwọ Olúwa àpáta mi, àti Olùdáǹdè mi.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-