Publicidade

Salmos 96

1 Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa,

ẹ kọrin sí Olúwa gbogbo ayé.

2 Ẹ kọrin sí Olúwa, yin orúkọ rẹ̀

ẹ sọ ti ìgbàlà rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́.

3 Ẹ sọ ti ògo rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè

àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrín gbogbo ènìyàn.

4 Nítorí títóbi ní Olúwa ẹni tí ìyìn tọ́ sí;

òun ní o yẹ kí a bẹ̀rù ju gbogbo òrìṣà lọ.

5 Nítorí asán ni gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè

ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.

6 Ọlá àti ọláńlá wà ní iwájú rẹ̀

agbára àti ògo wà ní ibi mímọ́ rẹ̀.

7 Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìbátan ènìyàn,

ẹ fi agbára àti ògo fún Olúwa.

8 Ẹ fi ògo tí ó tọ́ sí Olúwa fún un;

ẹ mú ọrẹ wá, kí ẹ sì wá sí àgbàlá rẹ̀.

9 Ẹ máa sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́ rẹ̀;

ẹ wárìrì níwájú rẹ̀ gbogbo ayé.

10 Sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, "Olúwa jẹ ọba."

A fi ìdí ayé múlẹ̀, tí kò sì lè yí;

ẹni tí yóò fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ ènìyàn.

11 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, kí ayé sì pariwo

jẹ́ kí pápá òkun kí ó hó pẹ̀lú ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀.

12 Jẹ́ kí oko kún fún ayọ̀, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀;

nígbà náà ni gbogbo igi igbó yóò máa yọ̀.

13 Wọn yóò kọrin níwájú Olúwa,

nítorí tí ó ń bọ̀ wá, ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé.

Yóò fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé

àti ti àwọn ènìyàn ni yóò fi òtítọ́ rẹ̀ ṣe.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_06-50-08-