Publicidade

Salmos 98

1 Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa,

nítorí tí ó ṣe ohun ìyanu;

ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti apá mímọ́ rẹ̀

o ṣe iṣẹ́ ìgbàlà fún un

2 Olúwa ti sọ ìgbàlà rẹ̀ di mí mọ̀

o fi òdodo rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdè.

3 Ó rántí ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ fún àwọn ará ilé Israẹli;

gbogbo òpin ayé ni ó ti rí

iṣẹ́ ìgbàlà Ọlọ́run wa.

4 Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Olúwa, gbogbo ayé,

ẹ bú sáyọ̀, ẹ kọrin ìyìn,

5 ẹ fi dùùrù kọrin sí Olúwa, pẹ̀lú dùùrù àti ìró ohùn orin mímọ́,

6 pẹ̀lú ìpè àti fèrè

ẹ hó fún ayọ̀ níwájú Olúwa ọba.

7 Jẹ́ kí òkun kí ó hó pẹ̀lú gbogbo

ohun tí ó wà nínú rẹ̀,

Gbogbo ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

8 Ẹ jẹ́ kí odo kí ó ṣápẹ́,

ẹ jẹ́ kí òkè kí ó kọrin pẹ̀lú ayọ̀;

9 ẹ jẹ́ kí wọn kọrin níwájú Olúwa,

nítorí tí yóò wá ṣèdájọ́ ayé

bẹ́ẹ̀ ni yóò ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè nínú òdodo

àti àwọn ènìyàn ní àìṣègbè pẹ̀lú.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-