Publicidade

Salmos 13

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

1 Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Ìwọ o ha gbàgbé mi títí láé?

Yóò tí pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa fi ojú rẹ pamọ́ fún mi?

2 Yóò ti pẹ́ tó tí èmi ó máa bá èrò mi jà,

àti ní ojoojúmọ́ ni èmi ń ní ìbànújẹ́ ní ọkàn mi?

Yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ọ̀tá mi yóò máa borí mi?

3 Wò mí kí o sì dá mi lóhùn, Olúwa Ọlọ́run mi.

Fi ìmọ́lẹ̀ fún ojú mi, kí èmi ó má sún oorun ikú.

4 Ọ̀tá mi wí pé, "Èmi ti ṣẹ́gun rẹ̀,"

àwọn ọ̀tá mi yóò yọ̀ tí mo bá ṣubú.

5 Ṣùgbọ́n mo gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà;

ọkàn mi ń yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.

6 Èmi ó máa kọrin sí Olúwa,

nítorí ó dára sí mi.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-