Publicidade

Salmos 33

1 Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo;

ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.

2 Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù;

ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.

3 Ẹ kọ orin tuntun sí i;

ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.

4 Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin,

gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.

5 Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́;

ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.

6 Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run,

àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.

7 Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò;

ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.

8 Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa:

jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.

9 Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀;

ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.

10 Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán;

ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.

11 Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé,

àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.

12 Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀,

àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.

13 Olúwa wò láti ọ̀run wá;

Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.

14 Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́

Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé

15 ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà,

ó sì kíyèsi ìṣe wọn.

16 A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun;

kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.

17 Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun;

bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.

18 Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,

àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.

19 Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú

àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.

20 Ọkàn wa dúró de Olúwa;

òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.

21 Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀,

nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.

22 Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa,

àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-