Publicidade

Salmos 26

Ti Dafidi.

1 Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa,

nítorí tí mo ti ń rìn nínú ìwà òtítọ́ ọ̀ mi,

mo sì ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa,

ǹjẹ́ ẹsẹ̀ mi kì yóò yẹ̀.

2 Wádìí mi wò, Ìwọ Olúwa, kí o sì dán mi wò,

dán àyà àti ọkàn mi wò;

3 nítorí ìfẹ́ ẹ̀ rẹ tí ó dúró ṣinṣin ń bẹ níwájú mi,

èmí sì ti rìn nínú òtítọ́ rẹ.

4 Èmi kò jókòó pẹ̀lú aláìṣòótọ́,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò bá àwọn àgàbàgebè wọlé.

5 Èmi ti kórìíra àwùjọ àwọn ènìyàn búburú

èmi kì yóò sì bá àwọn ènìyàn ìkà jókòó.

6 Èmí ó wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì yí pẹpẹ rẹ ká Olúwa.

7 Èmi yóò kọrin sókè àní orin ọpẹ́,

èmi yóò sì máa sọ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.

8 Háà Olúwa, èmí ń fẹ́ ilé rẹ níbi tí ìwọ ń gbé,

àní níbi tí ògo rẹ̀ wà.

9 Má ṣe gbá mi dànù pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,

tàbí ẹ̀mí mi pẹ̀lú àwọn ọkùnrin tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ,

10 àwọn tí ọwọ́ wọn kún fún ìwà ibi,

tí ọwọ́ ọ̀tún wọn kún fún àbẹ̀tẹ́lẹ̀.

11 Ṣùgbọ́n èmi ó máa rìn nínú ìwà títọ́;

rà mí padà, kí o sì ṣàánú fún mi.

12 Ẹsẹ̀ mi dúró lórí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú;

nínú ìjọ ńlá èmi yóò fi ìbùkún fún Olúwa.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-