Publicidade

Salmos 14

Fún adarí orin. Ti Dafidi.

1 Aṣiwèrè wí nínú ọkàn rẹ̀ pé,

"Ko sí Ọlọ́run."

Wọ́n díbàjẹ́, iṣẹ́ wọn sì burú;

kò sí ẹnìkan tí yóò ṣe rere.

2 Olúwa sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run wá

lórí àwọn ọmọ ènìyàn

bóyá ó le rí ẹni tí òye yé,

ẹnikẹ́ni tó ń wá Ọlọ́run.

3 Gbogbo wọn sì ti yípadà, gbogbo wọn sì ti díbàjẹ́;

kò sì ṣí ẹni tí ó ń ṣe rere,

kò sí ẹnìkan.

4 Ǹjẹ́ olùṣe búburú kò ha ní ìmọ̀?

Àwọn tí ó ń pa ènìyàn mi jẹ bí ẹní jẹun;

wọn kò sì ké pe Olúwa?

5 Wọ́n wà níbẹ̀, tí a bò mọ́lẹ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù,

nítorí Ọlọ́run wà ní àwùjọ àwọn olódodo.

6 Ẹ̀yin olùṣe búburú da èrò àwọn tálákà rú,

ṣùgbọ́n Olúwa ni ààbò wọn.

7 Ìgbàlà àwọn Israẹli yóò ti Sioni wá!

Nígbà tí Olúwa bá mú ìkólọ àwọn ènìyàn rẹ̀ padà,

jẹ́ kí Jakọbu kí ó yọ̀, kí inú Israẹli kí ó dùn!

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-