Publicidade

Jó 40

Jobu rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀

1 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,

2 "Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́?

Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!"

3 Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,

4 "Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà?

Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.

5 Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́;

lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́."

6 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,

7 "Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin,

èmi ó bi ọ léèrè,

kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.

8 "Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán?

Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.

9 Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run

tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?

10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́,

tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.

11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde;

kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.

12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀

kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.

13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀,

kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.

14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé,

ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.

15 "Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti,

tí mo dá pẹ̀lú rẹ,

òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.

16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ,

àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.

17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari,

iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.

18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ,

Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.

19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run;

síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.

20 Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá,

níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.

21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì,

lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.

22 Igi lótusì síji wọn bò o;

igi arọrọ odò yí i káàkiri.

23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ;

ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.

24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀,

tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-18_14-04-22-