Publicidade

Jó 28

Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n àti òye Jobu

1 Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ,

àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.

2 Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin,

bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.

3 Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn,

ó sì ṣe àwárí ìṣúra

láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.

4 Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè,

àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀,

wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.

5 Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá,

àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná;

6 òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta safire,

o sì ní erùpẹ̀ wúrà.

7 Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀,

àti ojú gúnnugún kò rí i rí.

8 Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí,

bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.

9 Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta,

ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.

10 Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta,

ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.

11 Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya,

ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.

12 Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí,

níbo sì ni òye ń gbe?

13 Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.

14 Ọ̀gbun wí pé, "Kò sí nínú mi";

omi òkun sì wí pé, "Kò si nínú mi."

15 A kò le è fi wúrà rà á,

bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òsùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.

16 A kò le è fi wúrà Ofiri, tàbí òkúta óníkìsì iyebíye,

tàbí òkúta safire díye lé e.

17 Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;

bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.

18 A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi;

iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.

19 Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;

bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.

20 Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá?

Tàbí níbo ni òye ń gbé?

21 A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo,

ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.

22 Ibi ìparun àti ikú wí pé,

àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.

23 Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀,

òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.

24 Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé,

ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,

25 láti dà òsùwọ̀n fún afẹ́fẹ́,

ó sì fi òsùwọ̀n wọ́n omi.

26 Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò,

tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,

27 nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde;

ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.

28 Àti fún ènìyàn ni ó wí pé,

"Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n,

àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye."

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-18_14-04-22-