Publicidade

Jó 37

Ọlọ́run kì í pọ́n ni lójú láìnídìí

1 "Àyà sì fò mi sí èyí pẹ̀lú,

ó sì kúrò ní ipò rẹ̀.

2 Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀, kí ẹ sì gbọ́ ìró ohùn rẹ̀,

àti èyí tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde wá.

3 Ó ṣe ìlànà rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ọ̀run gbogbo,

mọ̀nàmọ́ná rẹ̀ ni ó sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́ dé òpin ilẹ̀ ayé.

4 Lẹ́yìn mọ̀nàmọ́ná ohùn kan fọ̀ ramúramù;

ó sì fi ohùn ọláńlá rẹ̀ sán àrá.

Òhun kì yóò sì dá àrá dúró,

nígbà tí ó bá ń gbọ́ ohùn rẹ̀.

5 Ọlọ́run fi ohùn rẹ̀ sán àrá ní ọ̀nà ìyanu;

ohùn ńlá ńlá ni í ṣe tí àwa kò le mọ̀.

6 Nítorí tí ó wí fún yìnyín pé, ‘Ìwọ rọ̀ sílẹ̀ ayé,’

àti pẹ̀lú fún ọwọ́ òjò, ‘Fún òjò ńlá agbára rẹ̀.’

7 Ó fi èdìdì di ọwọ́ gbogbo ènìyàn kí gbogbo wọn kí ó lè mọ iṣẹ́ rẹ̀,

ó sì tún dá olúkúlùkù ènìyàn dúró lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀.

8 Nígbà náà ní àwọn ẹranko wọ inú ihò lọ,

wọn a sì wà ni ipò wọn.

9 Láti ìhà gúúsù ni ìjì àjàyíká tí jáde wá,

àti òtútù láti inú afẹ́fẹ́ ti tú àwọsánmọ̀ ká.

10 Nípa ẹ̀mí Ọlọ́run a fi ìdí omi fún ni,

ibú omi á sì súnkì.

11 Pẹ̀lúpẹ̀lú ó fi omi púpọ̀ mú àwọsánmọ̀ wúwo,

a sì tú àwọsánmọ̀ ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ká ara wọn.

12 Àwọn wọ̀nyí yí káàkiri nípa ìlànà rẹ̀,

kí wọn kí ó lè ṣe ohunkóhun

tí ó pàṣẹ fún wọn lórí ilẹ̀ ayé.

13 Ó mú àwọsánmọ̀ wá, ìbá ṣe fún ìkìlọ̀,

tàbí omi wá sí ayé láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.

14 "Jobu, dẹtí sílẹ̀ sí èyí;

dúró jẹ́ẹ́ kí o sì ro iṣẹ́ ìyanu Ọlọ́run.

15 Ṣe ìwọ mọ àkókò ìgbà tí Ọlọ́run ṣe wọ́n lọ́jọ̀,

tí ó sì mú ìmọ́lẹ̀ àwọsánmọ̀ rẹ̀ dán?

16 Ṣé ìwọ mọ ìgbà tí àwọsánmọ̀ í fò lọ,

iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀?

17 Ìwọ ẹni ti aṣọ rẹ̀ ti máa n gbóná,

nígbà tí ó fi atẹ́gùn ìhà gúúsù mú ayé dákẹ́.

18 Ìwọ ha ba tẹ́ pẹpẹ ojú ọ̀run, tí ó dúró ṣinṣin,

tí ó sì dàbí dígí tí ó yọ̀ dà?

19 "Kọ́ wa ní èyí tí a lè wí fún un;

nítorí pé àwa kò le wádìí ọ̀rọ̀ náà nítorí òkùnkùn wa.

20 A ó ha wí fún un pé, èmi fẹ́ sọ̀rọ̀?

Tàbí ẹnìkan lè wí pé, ìfẹ́ mi ni pé kí a gbé mi mì?

21 Síbẹ̀ nísinsin yìí ènìyàn kò rí

oòrùn tí ń dán nínú àwọsánmọ̀,

ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ń kọjá, a sì gbá wọn mọ́.

22 Wúrà dídán ti inú ìhà àríwá jáde wá;

lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ọláńlá ẹ̀rù ńlá wa.

23 Nípa ti Olódùmarè àwa kò le wádìí rẹ̀, ó rékọjá ní ipá;

nínú ìdájọ́ àti títí bi òun kì í ba ẹ̀tọ́ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òtítọ́ jẹ́.

24 Nítorí náà ènìyàn ha máa bẹ̀rù rẹ̀,

òun kì í ṣe ojú sájú ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́n ní ayé?"

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-18_14-04-22-