Publicidade

Jó 32

Ọ̀rọ̀ Elihu

1 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí dákẹ́ láti dá Jobu lóhùn, nítorí ó ṣe olódodo lójú ara rẹ̀. 2 Nígbà náà ni inú bí Elihu ọmọ Barakeli ará Busi, láti ìbátan ìdílé Ramu; ó bínú si Jobu nítorí ti ó dá ara rẹ̀ láre kàkà ki ó dá Ọlọ́run láre. 3 Inú sì bí i sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, nítorí tí wọn kò rí ọ̀nà láti dá Jobu lóhùn bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá Jobu lẹ́bi. 4 Ǹjẹ́ Elihu ti dúró títí tí Jobu fi sọ̀rọ̀ tán nítorí tí àwọn wọ̀nyí dàgbà ju òun lọ ní ọjọ́ orí. 5 Nígbà tí Elihu rí i pé ìdáhùn ọ̀rọ̀ kò sí ní ẹnu àwọn ọkùnrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí nígbà náà ni ó bínú.

6 Elihu, ọmọ Barakeli, ará Busi, dáhùn ó sì wí pé,

"Ọmọdé ni èmi,

àgbà sì ní ẹ̀yin;

ǹjẹ́ nítorí náà ní mo dúró,

mo sì ń bẹ̀rù láti fi ìmọ̀ mi hàn yin.

7 Èmi wí pé ọjọ́ orí ni ìbá sọ̀rọ̀,

àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ní ìbá kọ́ ni ní ọgbọ́n.

8 Ṣùgbọ́n ẹ̀mí kan ní ó wà nínú ènìyàn

àti ìmísí Olódùmarè ní ì sì máa fún wọn ní òye.

9 Ènìyàn ńlá ńlá kì í ṣe ọlọ́gbọ́n,

bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbà ní òye ẹ̀tọ́ kò yé.

10 "Nítorí náà ní èmí ṣe wí pé, ẹ dẹtí sílẹ̀ sí mi;

èmí pẹ̀lú yóò fi ìmọ̀ mi hàn.

11 Kíyèsi i, èmí ti dúró de ọ̀rọ̀ yín;

èmi fetísí àròyé yín,

nígbà tí ẹ̀yin ń wá ọ̀rọ̀ ti ẹ̀yin yóò sọ;

12 àní, mo fiyèsí yín tinútinú.

Sì kíyèsi i, kò sí ẹnìkan nínú yín tí ó le já Jobu ní irọ́;

tàbí tí ó lè dá a lóhùn àríyànjiyàn rẹ̀!

13 Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe wí pé, ‘Àwa wá ọgbọ́n ní àwárí;

Ọlọ́run ni ó lè bì í ṣubú kì í ṣe ènìyàn.’

14 Bí òun kò ti sọ̀rọ̀ sí mi,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi ọ̀rọ̀ yín dá a lóhùn.

15 "Ẹnu sì yà wọ́n, wọn kò sì dáhùn mọ́,

wọ́n ṣíwọ́ ọ̀rọ̀ í sọ.

16 Mo sì retí, nítorí wọn kò sì fọhùn, wọ́n dákẹ́ jẹ́ẹ́;

wọn kò sì dáhùn mọ́.

17 Bẹ́ẹ̀ ni èmí ó sì dáhùn nípa ti èmi,

èmí pẹ̀lú yóò sì fi ìmọ̀ mi hàn.

18 Nítorí pé èmi kún fún ọ̀rọ̀ sísọ,

ẹ̀mí ń rọ̀ mi ni inú mi.

19 Kíyèsi i, ikùn mi dàbí ọtí wáìnì, tí kò ní ojú-ìhò;

ó múra tán láti bẹ́ bí ìgò-awọ tuntun.

20 Èmí ó sọ, kí ara kí ó le rọ̀ mí,

èmí ó sí ètè mi, èmí ó sì dáhùn.

21 Lóòtítọ́ èmi kì yóò ṣe ojúsàájú sí ẹnìkankan,

bẹ́ẹ̀ ni èmí kì yóò sì ṣe ìpọ́nni fún ẹnìkan.

22 Nítorí pé èmí kò mọ̀ ọ̀rọ̀ ìpọ́nni í sọ ní ṣíṣe bẹ́ẹ̀,

ẹlẹ́dàá mi yóò mú mi kúrò lọ́gán.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-18_14-04-22-