Publicidade

Jó 6

Ìdáhùn Jobu

1 Jobu sì dáhùn ó si wí pé,

2 "Háà! À bá lè wọ́n ìbìnújẹ́ mi nínú òsùwọ̀n,

kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òsùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!

3 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìbá wúwo jú iyanrìn òkun lọ,

nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé.

4 Nítorí pé ọfà Olódùmarè wọ̀ mi nínú,

oró èyí tí ọkàn mi mú;

ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.

5 Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko,

tàbí ọ̀dá màlúù a máa dún lórí ìjẹ rẹ̀?

6 A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀,

tàbí adùn ha wà nínú funfun ẹyin?

7 Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò,

òun ni ó dàbí oúnjẹ tí ó mú mi ṣàárẹ̀.

8 "Háà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà;

àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.

9 Àní Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa mí run,

tí òun ìbá jẹ́ ṣíwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.

10 Nígbà náà ní èmi ìbá ní ìtùnú síbẹ̀,

àní, èmi ìbá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí:

nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.

11 "Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí?

Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?

12 Agbára mi ha ṣe agbára òkúta bí?

Ẹran-ara mi í ṣe idẹ?

13 Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi:

ọgbọ́n kò ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?

14 "Ẹni tí àyà rẹ̀ yọ́ dànù, ta ni a bá máa ṣàánú fún láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ wá,

kí ó má ba à kọ ìbẹ̀rù Olódùmarè sílẹ̀?

15 Àwọn ará mi dàbí odò tí kò ṣe gbẹ́kẹ̀lé

bí ìṣàn omi odò, wọ́n sàn kọjá lọ.

16 Tí ó dúdú nítorí omi dídì,

àti níbi tí yìnyín dídì gbé di yíyọ́.

17 Nígbàkígbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ sàn lọ,

nígbà tí oòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.

18 Àwọn oníṣòwò yà kúrò ní ọ̀nà wọn,

wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.

19 Ẹgbẹ́ oníṣòwò Tema ń wá omi,

àwọn oníṣòwò Ṣeba ń dúró dè wọ́n ní ìrètí.

20 Wọ́n káàárẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e;

wọ́n dé bẹ̀, wọ́n sì dààmú.

21 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin dàbí wọn;

ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.

22 Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá,

tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?

23 Tàbí, ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni,

tàbí, ẹ rà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì’?

24 "Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́

kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti ṣìnà.

25 Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tó

ṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbáwí yín jásí?

26 Ẹ̀yin ṣè bí ẹ tún ọ̀rọ̀ mi ṣe

àti ohùn ẹnu tí ó dàbí afẹ́fẹ́ ṣe àárẹ̀.

27 Àní ẹ̀yin ṣe gẹ́gẹ́ bí aláìní baba,

ẹ̀yin sì da iye lé ọ̀rẹ́ yín.

28 "Nítorí náà, kí èyí kí ó tó fún yín.

Ẹ má wò mi! Nítorí pé ó hàn gbangba pé,

ní ojú yín ni èmi kì yóò ṣèké.

29 Èmi ń bẹ̀ yín, ẹ padà, kí ó má sì ṣe jásí ẹ̀ṣẹ̀;

àní, ẹ sì tún padà, àre mi ń bẹ nínú ọ̀rọ̀ yìí.

30 Àìṣedéédéé ha wà ní ahọ́n mi?

Ǹjẹ́ ìtọ́wò ẹnu mi kò kúkú le mọ ohun ti ó burú jù?

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-18_14-04-22-