Publicidade

Jó 26

Ìdáhùn Jobu

1 Ṣùgbọ́n Jobu sì dáhùn wí pé,

2 "Báwo ni ìwọ ń ṣe ìrànlọ́wọ́ ẹni tí kò ní ipá,

báwo ní ìwọ ń ṣe gbe apá ẹni tí kò ní agbára?

3 Báwo ni ìwọ ń ṣe ìgbìmọ̀ fun ẹni tí kò ní ọgbọ́n,

tàbí báwo òye rẹ to pọ to bẹ́ẹ̀?

4 Ta ni ó ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,

àti ẹ̀mí ta ni ó gba ẹnu rẹ sọ̀rọ̀?"

5 "Àwọn aláìlágbára ti isà òkú wárìrì,

lábẹ́ omi pẹ̀lú àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

6 Ìhòhò ni ipò òkú níwájú Ọlọ́run,

ibi ìparun kò sí ní ibojì.

7 Òun ní o nà ìhà àríwá ọ̀run ní ibi òfúrufú,

ó sì so ayé rọ̀ ní ojú asán.

8 Ó di omi pọ̀ nínú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ̀ tí ó nípọn;

àwọsánmọ̀ kò sì ya nísàlẹ̀ wọn.

9 Ó sì fa ojú ìtẹ́ rẹ̀ sẹ́yìn,

ó sì tẹ àwọsánmọ̀ rẹ̀ sí i lórí.

10 Ó fi ìdè yí omi òkun ká,

títí dé ààlà ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn.

11 Ọ̀wọ́n òpó ọ̀run wárìrì,

ẹnu sì yà wọ́n sì ìbáwí rẹ̀.

12 Ó fi ipá rẹ̀ dààmú omi Òkun;

nípa òye rẹ̀, ó gé agbéraga sí wẹ́wẹ́.

13 Nípa ẹ̀mí rẹ̀ ni ó ti ṣe ọ̀run ní ọ̀ṣọ́;

ọwọ́ rẹ̀ ni ó fi dá ejò wíwọ́ nì.

14 Kíyèsi i, èyí ní òpin ọ̀nà rẹ̀;

ohùn èyí tí a gbọ́ ti kéré tó!

Ta ni ẹni náà tí òye àrá agbára rẹ̀ lè yé?"

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-18_14-04-22-