Publicidade

Jó 12

Ìdáhùn Jobu

1 Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé,

2 "Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà,

ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!

3 Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin;

èmi kò kéré sí i yín.

Àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?

4 "Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀,

tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn,

à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà!

5 Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà

gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.

6 Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù;

àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu,

àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.

7 "Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́,

àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.

8 Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ,

àwọn ẹja inú òkun yóò sì sọ fún ọ.

9 Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan wọ̀nyí pé,

ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?

10 Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà,

àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.

11 Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí

tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?

12 Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún,

àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.

13 "Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára;

òun ló ni ìmọ̀ àti òye.

14 Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́;

Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.

15 Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ;

Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.

16 Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun;

ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.

17 Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò

a sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.

18 Ó tú ìdè ọba

ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.

19 Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò

ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.

20 Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò

ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.

21 Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá

ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.

22 Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá

ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.

23 Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n;

òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.

24 Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé,

a sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.

25 Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀;

òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-18_14-04-22-