Publicidade

Salmos 8

Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Saamu ti Dafidi.

1 Olúwa, Olúwa wa,

orúkọ rẹ̀ ti ní ìyìn tó ní gbogbo ayé!

Ìwọ ti gbé ògo rẹ ga

ju àwọn ọ̀run lọ.

2 Láti ẹnu ọmọ ọwọ́ àti ọmọ ọmú

ni o ti yan ìyìn nítorí àwọn ọ̀tá rẹ,

láti pa àwọn ọ̀tá àti àwọn olùgbẹ̀san lẹ́nu mọ́.

3 Nígbà tí mo ro ọ̀run rẹ,

iṣẹ́ ìka rẹ,

òṣùpá àti ìràwọ̀,

tí ìwọ tí gbé kalẹ̀,

4 kí ni ènìyàn tí ìwọ ń rò nípa rẹ̀,

àní ọmọ ènìyàn tí ìwọ ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀?

5 Ìwọ ṣe é ní onírẹ̀lẹ̀ díẹ̀ ju Ọlọ́run lọ,

ìwọ sì dé e ní adé ògo àti ọlá.

6 Ìwọ mú un jẹ ọba lórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ;

ìwọ sì fi ohun gbogbo sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀:

7 àwọn agbo àgùntàn àti àwọn màlúù,

àti ẹranko igbó,

8 ẹyẹ ojú ọrun,

àti ẹja inú Òkun,

àti ohun tí ń wẹ nínú ipa Òkun.

9 Olúwa, Olúwa wa,

orúkọ rẹ ti ní ìyìn tó ní gbogbo ayé!

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-