Publicidade

Salmos 60

Fún adarí orin. Tí ohùn "Lílì ti Májẹ̀mú." Miktamu ti Dafidi. Fún ìkọ́ni. Nígbà tí ó bá Aramu-Naharaimu àti Siria-Soba jà, àti nígbà tí Joabu yípadà tí ó sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlá àwọn ará Edomu ní àfonífojì Iyọ̀.

1 Ìwọ ti kọ̀ wá sílẹ̀,

Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká,

ìwọ ti bínú nísinsin yìí, tún ara rẹ yípadà sí wa.

2 Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ;

mú fífọ́ rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mì.

3 Ìwọ ti fi ìgbà ewu han àwọn ènìyàn rẹ;

ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wá gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.

4 Àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ní ìwọ fi ọ̀págun fún

kí a lè fihàn nítorí òtítọ́. Sela.

5 Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́,

kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.

6 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀:

"Ní ayọ̀, èmi ó pọ Ṣekemu jáde

èmi ó sì wọ́n àfonífojì Sukkoti.

7 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase;

Efraimu ni àṣíborí mi,

Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.

8 Moabu ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi,

lórí Edomu ní mo bọ́ bàtà mi sí;

lórí Filistia ni mo kígbe ayọ̀."

9 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì?

Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Edomu?

10 Kì í ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀

tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?

11 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá,

nítorí asán ni ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.

12 Nípa Ọlọ́run ni a óò ní ìṣẹ́gun,

yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-