Publicidade

Salmos 15

Saamu ti Dafidi.

1 Olúwa, ta ni yóò máa ṣe àtìpó nínú àgọ́ rẹ?

Ta ni yóò máa gbé ní òkè mímọ́ rẹ?

2 Ẹni tí ń rìn déédé

tí ó sì ń sọ òtítọ́,

láti inú ọkàn rẹ̀;

3 tí kò fi ahọ́n rẹ̀ sọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn,

tí kò ṣe ibi sí aládùúgbò rẹ̀

tí kò sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí ẹnìkejì rẹ̀,

4 ní ojú ẹni tí ènìyànkénìyàn di gígàn

ṣùgbọ́n ó bọ̀wọ̀ fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa,

ẹni tí ó búra sí ibi ara rẹ̀

àní tí kò sì yípadà,

5 tí ó ń yá ni lówó láìsí èlé

tí kò sì gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lòdì sí aláìlẹ́ṣẹ̀.

Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe èyí

ni a kì yóò mì láéláé.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-