Publicidade

Zacarias 13

Ìwẹ̀nùmọ́ kúrò nínú ẹsẹ̀

1 "Ní ọjọ́ náà ìsun kan yóò ṣí sílẹ̀ fún ilé Dafidi àti fún àwọn ará Jerusalẹmu, láti wẹ̀ wọ́n mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àti àìmọ́ wọn.

2 "Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ni èmi ó gé orúkọ àwọn òrìṣà kúrò ni ilẹ̀ náà, a kì yóò sì rántí wọn mọ́, àti pẹ̀lú èmi ó mú àwọn wòlíì èké àti àwọn ẹ̀mí àìmọ́ kúrò ni ilẹ̀ náà. 3 Yóò sì ṣe, nígbà tí ẹnìkan yóò sọtẹ́lẹ̀ síbẹ̀, ni baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí ó bí í yóò wí fún un pé, ‘Ìwọ ki yóò yè, nítorí ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ èké ni orúkọ Olúwa.’ Àti baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí o bí í yóò gun un ni àgúnpa nígbà tí ó bá sọtẹ́lẹ̀.

4 "Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ojú yóò tí àwọn wòlíì èké olúkúlùkù nítorí ìran rẹ̀, nígbà tí òun ba tí sọtẹ́lẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò sì wọ aṣọ wòlíì onírun rẹ̀ tí o fi ń tan ní jẹ. 5 Ṣùgbọ́n òun o wí pé, ‘Èmi kí í ṣe wòlíì, àgbẹ̀ ni èmi; nítorí tí a ti fi mí ṣe ìránṣẹ́ láti ìgbà èwe mi wá.’ 6 Ẹnìkan ó sì wí fún un pé, ‘Ọgbẹ́ kín ní wọ̀nyí ni ẹ̀yìn rẹ?’ Òun o sì dáhùn pé, ‘Wọ̀nyí ni ibi tí a ti sá mi ní ilé àwọn ọ̀rẹ́ mi.’

A lu olùṣọ́-àgùntàn, agbo ẹran fọ́nká

7 "Dìde, ìwọ idà, sí Olùṣọ́-àgùntàn mi,

àti sí ẹni tí í ṣe ẹnìkejì mi,"

ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:

"Kọlu Olùṣọ́-àgùntàn,

àwọn àgùntàn a sì túká:

èmi o sì yí ọwọ́ mi sí àwọn kéékèèké.

8 Yóò sì ṣe, ni gbogbo ilẹ̀," ni Olúwa wí,

"a ó gé apá méjì nínú rẹ̀ kúrò yóò sì kú;

ṣùgbọ́n apá kẹta yóò kù nínú rẹ̀.

9 Èmi ó sì mú apá kẹta náà la àárín iná,

èmi yóò sì yọ́ wọn bí a ti yọ́ fàdákà,

èmi yóò sì dán wọn wò, bi a tí ń dán wúrà wò:

wọn yóò sì pé orúkọ mi,

èmi yóò sì dá wọn lóhùn:

èmi yóò wí pé, ‘Àwọn ènìyàn mi ni,’

àwọn yóò sì wí pé, ‘Olúwa ni Ọlọ́run wa.’ "

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-