Publicidade

Salmos 23

Saamu ti Dafidi.

1 Olúwa ni olùṣọ́ èmi àgùntàn rẹ̀, èmi kì yóò ṣe aláìní.

2 Ó mú mi dùbúlẹ̀ sí ibi pápá oko tútù,

Ó mú mi lọ sí ibi omi dídákẹ́ rọ́rọ́,

3 Ó mú ọkàn mi padà bọ̀ sípò.

Ó mú mi lọ sí ọ̀nà òdodo

nítorí orúkọ rẹ̀.

4 Bí mo tilẹ̀ ń rìn

láàrín àfonífojì òjìji ikú,

èmi kì yóò bẹ̀rù ibi kan,

nítorí ìwọ wà pẹ̀lú mi;

ọ̀gọ rẹ àti ọ̀pá à rẹ,

wọ́n ń tù mí nínú.

5 Ìwọ tẹ́ tábìlì oúnjẹ sílẹ̀ níwájú mi

ní ojú àwọn ọ̀tá à mi.

Ìwọ ta òróró sí mi ní orí;

ago mí sì kún àkúnwọ́sílẹ̀.

6 Nítòótọ́, ìre àti àánú ni yóò máa tọ̀ mí lẹ́yìn

ní ọjọ́ ayé è mi gbogbo,

èmi yóò sì máa gbé inú ilé Olúwa

títí láéláé.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-