Publicidade

Salmos 28

Ti Dafidi.

1 Ìwọ Olúwa,

mo ké pe àpáta mi.

Má ṣe kọ etí dídi sí mi.

Tí ìwọ bá dákẹ́ sí mi,

èmí yóò dàbí àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun.

2 Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi fún àánú,

bí mo ṣe ń ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́,

bí mo ṣe gbé àwọn ọwọ́ mi sókè

sí Ibi Mímọ́ rẹ Jùlọ.

3 Má ṣe fà mí lọ pẹ̀lú ènìyàn búburú àti,

pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀,

tí ń sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò wọn

ṣùgbọ́n tí ìwà ìkà ń bẹ nínú wọn.

4 San ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn

àti fún iṣẹ́ ibi wọn;

gba ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn;

kí o sì san ẹ̀san wọn bí ó ti tọ́.

5 Nítorí pé wọn kò ka iṣẹ́ Olúwa sí,

tàbí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀

òun ó rún wọn wọlẹ̀

kì yóò sì gbé wọn ró mọ́.

6 Alábùkún fún ni Olúwa!

Nítorí pé ó ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.

7 Olúwa ni agbára mi àti asà mi;

nínú rẹ̀ ni mo gbẹ́kẹ̀lé; àní, ó sì ràn mí lọ́wọ́.

Ọkàn mi sì gbé sókè fún ayọ̀

àní pẹ̀lú orin mi mo fi ọpẹ́ fún un.

8 Olúwa ni agbára àwọn ènìyàn rẹ̀

òun ni odi ìgbàlà àwọn ẹni àmì òróró rẹ̀.

9 Ìwọ gba àwọn ènìyàn rẹ là, kí o sì bùkún àwọn ajogún rẹ;

di olùṣọ́-àgùntàn wọn, kí o sì gbé wọn lékè títí ayérayé.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-